Bùkọ́là Sàràkí

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Bukola Saraki, osu kẹwàá ọdún 2017

Olubukola Abubakar Saraki (tí wọ́n bí ní Ọjọ́ kọkàndínlógún oṣù Kejìlá ọdún 1962) jẹ́ òṣèlú àti Ààrẹ ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà orílẹ̀ èdè Nàìjíríà láti ìpínlẹ̀ Kwara. Ó ti fìgbà kan jẹ gómìnà ìpínlẹ̀ Kwara fún ọdún mẹ́jọ gbáko, bẹ̀rẹ̀ lọ́dún 2003 di 2011 lábẹ́ àsíyá ẹgbẹ́ òṣèlú People's Democratic Party, PDP. Ní kété tí ó fipò gómìnà sílẹ̀ lọ́dún 2011, wọ́n dibò yàn án sì ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà láti ṣojú ẹkùn ìdìbò àárín-gbùngbùn Ìpínlẹ̀ Kwara, bákan náà lọ́dún 2015,ó tún wọlé lẹ́ẹ̀kejì ṣùgbọ́n lábẹ́ àsíyá ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress, APC. Ó pàdánù ìdìbò láti padà sí ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà ni ẹ̀kẹta lọ́dún 2019, nígbàtí ó digbá-dagbọ̀n rẹ̀ kúrò ní APC, tí ó sì padà sí PDP, ègbé òṣèlú rẹ̀ àná.[1] Lásìkò yìí náà, ó díje dípò Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà lábẹ́ ẹgbẹ́ òṣèlú PDP, ṣùgbọ́n, ìdìbò abẹ́lé kò gbè ẹ. Igbá-kejì Ààrẹ-àná, Atiku Abubakar ni ẹgbẹ́ PDP fà kalẹ̀.[2] [3] [4] [5]

Ìgbé-ayé rẹ̀ nígbà èwe àti aáyán ẹ̀kọ́ kíkà rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́n bí Bùkọ́lá Sàràkí lọ́dún 1962 ní orílè èdè Bìrìtìkó (United Kingdom). Àgbà òṣèlú àti Sínétọ̀ ni bàbá tó bí i lọ́mọ, Olúṣọlá Sàràkí lọ́dún 1979 sí 1983. Florence Morẹ́nikẹ̀ Sàràkí lórúkọ Ìyá rẹ̀. Ìdílé atàpátadìde pọ́ńbélé ló ti wá. Ní ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀kọ́ kíkà rẹ̀, ó lọ sí Corona School, ní Victoria Island, Ìlú Èkó, ní ìlú Èkó kí ó tó tẹ̀síwájú ní ilé-ìwé gíga ti King's College, ní ìlú Èkó bákan náà lọ́dún 1973 sí 1978. Lẹ́yìn èyí, ó tún tẹ̀síwájú ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní ilé-ìwé Cheltenham College ní orílè-èdè United Kingdom lọ́dún 1979 to 1981, ibẹ̀ ló ti gba ìwé-ẹ̀rí ẹ̀kọ́ gíga rẹ̀. Ó tẹ̀síwájú nínú ẹ̀kọ́ síi ní London Hospital Medical College of the University of London lọ́dún 1982 sí 1987, níbi tí ó ti gba ìwé ẹ̀rí dókítà àṣẹ wòsàn M.B.B.S (London).[6] [7]

Ìgbé ayé rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Toyin Sàràkí ni orúkọ ìyàwó Bukola Saraki. Ọmọ mẹ́rin ni wọ́n bí fún ara wọn. Ní sáà rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí gómìnà ìpínlẹ̀ Kwara, wọ́n fi í joyè Tùràkí tí gbogbo àwọn Fúlàní. Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Ọba ìlú Ìlọrin tún fi í joyè Waziri tí gbogbo Ìlọrin, oyè Waziri dàbí òye Ààrẹ-ìlú, (Prime Minister). Bàbá rẹ̀, Olúṣọlá Sàràkí ló joyè náà kí Bùkọ̀lá Sàràkí tó jẹ ẹ́. Bákan náà, Olúbàdàn tí ìlú Ìbàdàn, Oba Sálíù Adétúnjí tún fi í joyè Ajagùnnà tí ìlú Ìbàdàn lọ́dún 2017. [8]

Àwọn Ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. "2019 Election: Saraki loses Senate seat to APC’s Oloriegbe". Punch Newspapers. 2015-12-15. Retrieved 2019-11-18. 
  2. Published (2015-12-15). "UPDATED: Saraki declares his intention to run for presidency". Punch Newspapers. Retrieved 2019-11-18. 
  3. vanguard; vanguard (2018-10-16). "Saraki named Atiku’s Presidential Campaign Council DG". Vanguard News. Retrieved 2019-11-18. 
  4. "Governor Bukola Saraki - Home". bukisaraki.org. 2010-04-08. Archived from the original on 2010-04-08. Retrieved 2019-11-18. 
  5. "COLUMBIA, SC". Who's On The Move. 2018-10-04. Retrieved 2019-11-18. 
  6. Odunayo, Adams (2015-09-21). "Passport Linked To Saraki Forged – UK Authority". Legit.ng - Nigeria news. Retrieved 2019-11-18. 
  7. "Bukola Saraki: Profile Of An Ambitious Political Gatekeeper". The Guardian Nigeria News - Nigeria and World News. 2015-05-03. Retrieved 2019-11-18. 
  8. "Saraki, 15 Others Get Chieftaincy Titles". Information Nigeria. 2017-03-04. Retrieved 2019-11-18.