M. K. O. Abíọ́lá
| Moshood Abiola | |
|---|---|
| Ọjọ́ìbí | 24 Oṣù Kẹjọ 1937 Abeokuta |
| Aláìsí | 7 July 1998 (ọmọ ọdún 60) Abuja |
| Orílẹ̀-èdè | Nàìjíríà |
| Orúkọ míràn | M.K.O Ab́iọ́lạ́ |
| Iṣẹ́ | Okowo, Oloselu, Oluranilowo. |
| Gbajúmọ̀ fún | Being arrested following a Presidential election in Nigeria which he won/Philanthropy |
| Olólùfẹ́ | Simbiat Atinuke Shoaga Kudirat Olayinka Adeyemi Adebisi Olawunmi Oshin Doyinsola Abiola Aboaba Modupe Onitiri-Abiola [1] Remi Abiola (+other women) |
| Àwọn ọmọ | Abdulateef Kola Abiola Dupsy Abiola Hafsat Abiola Rinsola Abiola Khafila Abiola (+other children) |
Moshood Káṣìmawòó Ọláwálé Abíọ́lá (August 24, 1937 - July 7, 1998) tí[2] ó túmọ̀ sí M.K.O Abíọ́lá jẹ́ ọmọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà. A bi ní ìlú Abẹ́òkúta ní Ìpínlẹ̀ Ògùn. Ó jẹ́ oníṣòẁò,òǹtẹ̀wé, olóṣèlú àti olóyè ilẹ̀ Yorùbá Ẹ̀gbá pàtàpátá.[3] Ó díje sí ipò Ààrẹ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ní ọdún 1993, òun náà sì ni gbogbo ènìyàn gbàgbọ́ tí wọ́n sì fẹnukò sí jákè-jádò orílẹ-èdè Nàìjíríà wípé ó jáwé olúborí nígbà tí olóri ìjọba ológun ìgbà náà Ibrahim Babangida kò kéde rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olúborí ètò ìdìbò náà tí ó sì tun fi ẹ̀sùn àìṣòtítọ́ àti àìṣòdodo ètò ìdìbò kan.
M.K.O ku ní ọjọ́ keje, oṣù kẹjọ, ọdún 1998. Ìṣẹ̀lẹ̀ ikú rẹ̀ ya ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn lẹ́nu nítoríwípé ó bọ́ sí ọjọ́ tí wọ̀n ti kéde wípé wọn ó túu sílẹ̀ nínú àhámọ́ tí ìjọba ológun tí ó wà ní orí àpèrè nì ìgbà náà fi pamọ́ sì. Wọ́n kéde wípé ó kú sí ilé ìwòsàn lẹ́yìn àìsàn ráńpẹ́. [4][5]
Igbesi Aye re
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Moshood Abíọ́lá ni àkọ́bí bàbá àti ìyá rẹ̀ lẹ́yìn ìkúnlẹ̀ ọmọ kẹtàlélógún (23), ìdí èyí ní ó fàá tí wọ́n fi dúró títí di ẹ̀yìn ọdún mẹ́ẹ̀dógún (15 years) kí àwọn òbí rẹ̀ tó fún lórúkọ rẹ̀ “Kasimawo”[6] . Moshood fakọyọ nínú ìmọ̀ ìdágbálé (entrepreneur) láti ìgb̀a èwe rẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ igi-ṣíṣẹ́ tà láti ọmọ ọdún mẹ́sàán. Ó ma ń jí ní ìdájí lọ sóko igi láti wá igi tí yóò tà ṣáájú kí ó tó lọ sị́ ilé-ìwé kí òun àti bàbá rẹ̀ tó ti rúgbo pẹ̀lú àwọn àbúrò rẹ̀ tó lè ri ówó ná. Nígb̀a tí ó t́o ọmọ ọdún mẹ́ẹ̀dógún (15 years), ó dá ẹgbẹ́ eré kan kalẹ̀ tí wọ́n ma ń kọrin kiri láti lè rí óúnjẹ jẹ níbi ìnáwo èyíkéyìí tí wọ́n bá lọ. Kò pẹ́, ó di gbajú-gbajà níbi orin rẹ̀ tó ń kó kiri, ó sì di ẹni tí ó ń bèerè fún owó iṣẹ́ kí wọ́n tó kọrin lóde ìnáwó . Àwọn owó tí ó ń rí níbi eré rẹ̀ yìí nị́ ó fi ń ran ẹbí rẹ̀ lọ́wọ́ tí ó sì ń san owó ilé-ẹ̀kọ́ gíga tí ìjọ Onítẹ̀bọmi tí ó wà ní Abéòkúta . Abíọ́́lá jẹ́ Olóòtú ìwé ìròyìn ọ̀sọ̀ọ̀sẹ̀ ilé-ìwé wọn tí ó ń jẹ́ The Trumpeter tí Olúṣẹ́gun Ọbásanjọ́ sì jẹ́ igbákejì rẹ. Ó dára pọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ National Council of Nigeria and the Cameroons ní ìgbà tí ó di ọmọ ọdún mọ́kàndínlógún nítorí ìfẹ́ tí ó ní sí ètò òṣèlú àwa arawa ó darapọ́ mọ́ ẹgbẹ́ òṣèlú Action Group[7], eléyìí tí olóògbè Ọbáfẹ́mi Awólọ́wọ̀ jẹ́ olùdásílẹ̀ rẹ̀
Ní ọdún 1960, Moshood jẹ àǹfàníi ẹ̀kọ́ ọ̀fẹ́ ti ijọba láti lọ ka ìwé ní University ti Glasgow ní ìlú Scotland ni ibi tí ó ti gba oyè nínú ìmọ̀ ìṣirò. Moshood jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọ ẹgbẹ́ Institute of Chartered Accountants of Nigeria (ICAN).
Àwọn ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ "REMEMBERING ABIOLA, 15 YEARS AFTER". National Mirror. July 6, 2013. Archived from the original on March 27, 2017. https://web.archive.org/web/20170327080631/http://nationalmirroronline.net/new/remembering-abiola-15-years-after/. Retrieved March 26, 2017.
- ↑ "Chief Moshood Kahimawo Olawale Abiola (MKO Abiola)". Africa Confidential. 2025-09-25. Retrieved 2025-09-25.
- ↑ "Moshood Kashimawo Olawale Abiola | Nigerian entrepreneur and politician". Encyclopedia Britannica (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2020-05-25.
- ↑ "‘MKO Was The Winner’ - Buhari Apologises To Abiola Family Over Annulment Of June 12 ’93 Election". Sahara Reporters. 2018-06-12. Retrieved 2018-06-13.
- ↑ Aribisala, Femi (2018-06-12). "What June 12 reveals about Nigerian democracy". Vanguard News. Retrieved 2018-06-13.
- ↑ Odumakin, Yinka (2018). "June 12 dissemblers". Vanguard News.
- ↑ Inyang, Ifreke (2018-06-12). "MKO Abiola: What Falana told Buhari about results of June 12 elections". Daily Post Nigeria. Retrieved 2018-06-13.