Segun Awolowo

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Segun Awolowo

Ṣẹ́gun Awólọ́wọ̀
Ààrẹ National Trade Promotion Organisation
Lọ́wọ́lọ́wọ́
Ó gun orí àga
2021
PresidentJean-Claude Brou
Executive Director of the Nigerian Export Promotion Council
In office
February 2018 – November 2021
ÀàrẹMuhammadu Buhari
In office
November 2013 – November 2017
ÀàrẹGoodluck Jonathan
Muhammadu Buhari
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí
Olusegun Awolowo Jr.

27 Oṣù Kẹ̀sán 1963 (1963-09-27) (ọmọ ọdún 60)
Ọmọorílẹ̀-èdèNigerian
Education
ProfessionLawyer

Olúṣẹ́gun Awólọ́wọ̀ Jr. (wọ́n bí i ní 27 September 1963), jẹ́ agbẹjọ́rò ọmọ nàìjíríà, ó jẹ́ Alákòóso Àgbà fún Nigerian Export Promotion Council, láti ọdún 2013 dé ọdún 2021 .[1][2]. Ó jẹ́ ọmọ-ọmọ àgbà Olóṣèlù Nàìjíríà nnì, Olóyè Obafemi Awolowo .[3] Ní oṣù keje ọdún 2021, wọ́n panupọ̀ dìbò yàn-án gẹ́gẹ́ bí i ààrẹ àwọn àjọ tóń ṣe ìgbélárugẹ fún òwò ní orílẹ̀ èdè yìí (TPOs) láti ara ECOWAS member States.[4][5]

Ìbẹ̀rẹ̀ Ayé Rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́n bí Awólọ́wọ̀ ní 27 September 1963, bàbá rẹ̀ (Ṣẹ́gun Awólọ́wọ̀ Sr.) kú ní 1965 ní ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n láti ara ìjàm̀bá ọkọ̀ ní òpópó márosẹ̀ ìbàdàn sí Èkó àtijọ́ [6] . Ẹ̀yìn oṣù méjì tí bàbá rẹ̀ kú ni wọ́n bí i [7], ọ̀dọ̀ Ẹ̀gbọ́n Bàbá rẹ̀ ni ó gbé ka ilé ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀, Abilékọ Tola Oyediran (nee Awolowo) àti ọkọ rẹ̀, Ọ̀jọ̀gbọ́n Kayode Oyediran. Kí ó tó dìgbà náà, ó gbé lọ́dọ̀ ìyá rẹ̀ àti àwọn tòun ti àwọn ẹ̀gbọ́n àti àbúrò rẹ̀.[8]

Ẹ̀kọ́[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Awólọ́wọ̀ bẹ̀rẹ̀ ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní Mayhill Convent School tòun ti Dolapo Osinbajo, ìyàwó igbákejì ààrẹ Yemi Osinbajo,lábẹ̀ àmójútó Ọ̀jọ̀gbọ́n àti Mrs Oyediran. láti ibẹ̀ , ó tẹ̀ síwájú lọ sí Igbobi College, Yaba, Ìpínlẹ̀ Èkó (Lagos State) fún ẹ̀kọ́ sẹ́kọ́ńdírì tí ó sì parí ẹ̀kọ́ sẹ́kọ́ńdírí rẹ̀ ní Government College, Ibadan. Lọ́gán tí ó parí ẹ̀kọ́ sẹ́kọ́ńdírì rẹ̀ ni ó tẹ̀síwájú lọ sí Ogun State University (now Olabisi Onabanjo University), Ago Iwoye tí ó sì kẹ́kọ̀ọ́ jáde pẹ̀lú oyè ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ LLB. [9]

Iṣẹ́[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Awolowo ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ilé iṣẹ́ amòfin Abayomi Sogbesan & Co. àti ilé iṣẹ́ amòfin ti GOK Ajayi & Co. lẹ́yìn ìgbà tí ó wọ àwùjọ àwọn agbẹjọ́rò ní oṣù kejìlá ọdún 1989. Ó ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìjọba President Olusegun Obasanjo's gẹ́gẹ́ bí Olùrànlọ́wọ́ Pàtàkì lórí àwọn ohun tó jẹ mọ́ àbàláyé, ètò àti ọ̀rọ̀ òfin. [10]

Ó ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìjọba Umaru Musa Yar'Adua gẹ́gẹ́ bí Olùrànlọ́wọ́ Pàtàkì tí ó sì ṣiṣẹ́ ní agbègbè ìjọba Àpapọ̀ gẹ́gẹ́ bí i akọ̀wé fún ètò ìdàgbàsókè àwùjọ àti Akọ̀wé fún ètò ìrìnà ọkọ̀ láti 2007 di 2011. Ó padà sí ìdí iṣẹ́ òfin rẹ̀ lẹ́yìn ètò ìdìbò ọdún 2011 títí di 2013 tí Ààrẹ t Goodluck Jonathan yàn-án sí ipò Alákòóso àgbà fún ilé iṣẹ́ Nigerian Export Promotion Council[11] tí iṣẹ́ rẹ̀ sì tẹnubodò ní ọdún 2017, oṣù kọkànlá ṣùgbọ́n Ààrẹ Muhammadu Buhari tún tún-un yàn sí ipò yìí kan náà ní Oṣù kejì 2018 fún sáà ọdún mẹ́rin mìíràn.[12][13]

Ìgbésí Ayé[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Awólọ́wọ̀ ní ìyàwó pẹ̀lú àwọn ọmọ. Ọmọbìnrin rẹ̀ Ṣeun jẹ́ ọlọ́rọ̀ ìyànjú tí ó sì ń darí ilé iṣẹ́ kan tí kìí ṣe ti ìjọba tí à ń pè ní Teach-A-Girl Nigeria. Èyí tí ó gbájú mọ́ ẹ̀kọ́ àwọn ọmọbìnrin ní Nigeria. Òun yìí kan náà ni Òlùdásílẹ̀ Leads Africa àti 3D Living Moments.[14]

Àwọn Ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. Ehikioya, Augustine (26 September 2018). "Buhari greets Awolowo at 55". The Nation Online. https://thenationonlineng.net/buhari-greets-awolowo-at-55/. Retrieved 30 June 2019. 
  2. Usigbe, Leon (26 September 2018). "Buhari Greets Awolowo At 55". Tribune. Archived from the original on 30 June 2019. https://web.archive.org/web/20190630145327/https://tribuneonlineng.com/166062/. Retrieved 30 June 2019. 
  3. Babarinsa, Dare (25 November 2015). "The woman who gave us Awolowo". guardian.ng. Guardian. https://www.guardian.ng/opinion/the-woman-who-gave-us-awolowo/amp. Retrieved 30 June 2019. 
  4. Anonymous (16 July 2021). "Buhari Congratulates Olusegun Awolowo On Election As President Of ECOWAS TPOs". Daily Trust. https://dailytrust.com/buhari-congratulates-olusegun-awolowo-on-election-as-president-of-ecowas-tpos. 
  5. "President Buhari Congratulates Olusegun Awolowo on Election to Lead Trade Promotion Organisations in West Africa". 16 July 2021. 
  6. Rilwan (18 July 2018). "Remembering Segun Awolowo". The Nation Newspaper. The Nation Newspaper. https://www.thenationonlineng.net/remembering-segun-awolowo/amp/. Retrieved 30 June 2019. 
  7. Lasisi, Akeem (25 July 2002). "Nigeria: Battle for Late Sage Obafemi Awolowo's Estate". All Africa. https://allafrica.com/stories/200207250357.html. Retrieved 30 June 2019. 
  8. Aworinde, Tobi (29 July 2018). "Years after dad's death, they would say he had gone to England – Segun Awolowo Snr's daughter, Funke". Punch Nigeria. https://www.punchng.com/years-after-dads-death-they-would-say-he-had-gone-to-england-segun-awolowo-snrs-daughter-funke/amp/. Retrieved 30 June 2019. 
  9. Aworinde, Tobi (29 July 2018). "Years after dad's death, they would say he had gone to England – Segun Awolowo Snr's daughter, Funke". Punch Nigeria. https://www.punchng.com/years-after-dads-death-they-would-say-he-had-gone-to-england-segun-awolowo-snrs-daughter-funke/amp/. Retrieved 30 June 2019. 
  10. "Olusegun Awolowo | NBASBL Conference 2019 .::. The 13th Annual Business Law Conference". www.nbasblconference.org. Archived from the original on 2019-07-04.  Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  11. "Olusegun Awolowo - TradewithAfrica". 
  12. Press Release (28 February 2018). "Buhari reappoints Segun Awolowo as NEPC Chief Executive Officer". Premium Times. https://www.premiumtimesng.com/news/more-news/260137-buhari-reappoints-segun-awolowo-nepc-chief-executive-officer.html. Retrieved 30 June 2019. 
  13. Olowolagba, Fikayo (28 February 2018). "Buhari re-appoints Segun Awolowo as NEPC boss". Daily Post. https://dailypost.ng/2018/02/28/buhari-re-appoints-segun-awolowo-nepc-boss/. Retrieved 30 June 2019. 
  14. Anonymous (2 March 2019). "Segun Awolowo picks new date for daughter's wedding". Sun Newspaper. https://www.sunnewsonline.com/segun-awolowo-picks-new-date-for-daughters-wedding/. Retrieved 30 June 2019.