Ọjà Ẹrù Veléketé

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Ọjà Ẹrù Veléketé jẹ́ ọjà tí ó wà ní ÀgbádárìgìÌpínlẹ̀ Èkó.[1] Ọjà yí ni wón dá sílẹ̀ ní ọdún 1502 tí wọ́n sì wá a fi orúkọ òrìsà Veléketé pe ọjà yíi.[2] Ọjà yí ṣe pàtàkì ní àkókò ìṣòwò ẹrù ti Trans-Atlantic ní Àgbádárìgì nítorípé ọjà yí dúró gégé bí ibi ààyè ìṣòwò níbití àwọn aláròóbọ̀, tí ó ma ńgba ẹrù tà, láti ilẹ̀ Áfíríkà ti má ńta àwọn ẹrù fún àwọn oníṣòwò ẹrù tí wón wá láti ìlú Yúrópù. Èyí ló mú kí ọjà yí jé òkan nínú àwọn ọjà ẹrù tí ènìyàn inú rẹ pọ̀ jùlọ ní Ìwọòrùn Áfíríkà.[3]

Ní ọdúnun 1805, Scipio Vaughan tí ó jẹ́ ọmọ abínibí Òwu ní Abéòkúta, orílè-èdè Nàìjíríà, ni àwọn oníṣòwò ẹrù ti trans-Atlantic tí ó jẹ́ ilé Yúrópù mú, tí wọ́n sì gbe e lọ sí Ọjà Ẹrú Veléketé ní Àgbádárìgì papọ́ pẹlú àwọn ẹrù miiran tí wón ti mú síwájú kí wọ́n tó wa fíi sínú ọkọ̀ ojú-omi tí wọn fi nkó àwọn ẹrù lọ sí ìlú Améríkà.[4] .

Oja Ẹrú, Badagry

Velekete ọjà ẹrú ni ọjà ará tí ó wà ní ìlú àgbádárìgì, ní Ìpínlẹ̀ Èkó.[5] Wọ́n da ọjà òwò ẹrú yí sílẹ̀ ní ọdún 1502, wọ́n sọ orúkọ ọjà yí ní Velekete tí ó jẹ́ orúkọ òrìṣà omi ati afẹ́fẹ́.[6]Ọjà yí gbajúmọ̀ gidi ní àsìkò owó ẹrú káàkiri Trans-Atlantic Slave trade, ó sì tún jẹ́ ojúkojú tí àwọn abáni rẹrú ti ma ń dúná dúrá pẹ̀lú olówó ẹrú tí ó f2lẹ́ ta ará fún àwọn Gẹ̀ẹ́sì, èyí mú kí ọjà yí gbajúmọ̀ káàkiri ilẹ̀ Ìwọ̀ Oòrùn Áfíríkà.[7]

Bí ó ṣe bẹ̀rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Dídé tí ọ̀gbẹ́ni kan olówò ẹrú tí ó jẹ́ ọmọ orílẹ̀-èdè Dutchland tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Hendrik Hertog tí wọ́n sábà ma ń da pe ní Yoo Huntokonu dé sí ìlú agbádárìgì ni ó gba àwọn lààmì-laaka ọmọ onílẹ̀ níyànjú pe kí wọ́n dá ọjà tí wọn yóò w ti ma ta àwọn ẹrú wọn, wọ́n sì da ọjà náà sílẹ̀ tí wọ́n pèé ní Velekete. Ó gba ilẹ̀, ó sì di dá ọjà yí sílẹ̀ tí àwọn olówò-ẹrú bíi tìrẹ̀ sì wá ń fi àwọn ohun tí wọ́n ní ṣe pàṣípàrọ̀ fún ọmọ èèyan gẹ́gẹ́ bí ará. Èyí kò ṣàdédé rí bẹ́ẹ̀ bí kò ṣe wípé àwọn olóyè ati àwọn alẹ́nu-lọ́rọ̀ àwùjọ ń rọ́wọ́ pọ́n lá níbi okòwò náà. Ọjà yí gbèrú nígbà tí àwọn òntajà àti ònrajà ti gbọ́ ara wọn yé, tí wọ́n sì ti mọ adùn tí ó wà nínú òwò wọn ati bí awọn aláwọ̀ funfun ṣe nílò òṣìṣẹ́ sí nínú oko ìrèkè wọn.[8]

Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ mále gbàgbé tí ó ti wáyé níbẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Canon, Oja Ẹrú, Badagry

Ní ọdún 1805, àwọn èèbó gẹ̀ẹ́sì mú Scipio Vaughan ẹni tí ó jẹ́ ará ìlú Òwu lẹ́rú, wọ́n sì kó òun àti àwọn mélòó kan tí wọ́n jọ kó lẹ́rú pọ̀ lọ tà ní ọjà Velekete ní ìlú àgbádárìgì, tí wọ́n sì gba ibẹ̀ di ẹrú ní ilẹ̀ Amẹ́ríkà.[9] Wọ́n tún ma ń kó àwọn ẹrú lótíṣiríṣi wà láti àwọn ìlú bí ibintí a mọ̀ sí Ìpínlẹ̀ Abia lóní wá tà ní ọjà Velekete. Wọ́n kọ́ túbú kékeré kan sí ọ̀gangan apá kejì ọjà náà tí wọ́n ti wọ́n ma ń tọ́júbẹrú sí di ọjọ́ ọjà ẹrú. Ọjọ́ márùn un márùn ún ni wọ́n nọ́jà ẹrú náà. Àwọn gèèbó yóò ma kò àwọn nkan bí dígí, àhàyá,ẹ̀tù ìbọn abọ́ ìjẹun, ọtí wisikí, àbùradà ati bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ.[10] Àmọ́ bí báyí, ọjà Velekete ti di àyè tí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ àti àrìnrì-àjò ìgbafẹ́ ma ń wá bẹ̀ wò fún àwọn tí wọ́n bá fẹ́ mọ kúlẹ̀ kúlẹ̀ nípa bí òwò ẹrú ṣe gbóná tó ní àárín gbungbun ilẹ̀ Áfíríkà.

Lára àwọn ibùdó tí ó ṣe pàtàkì nínú ìtàn òwò ẹrú náà ni_:[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  • ìdílé Mo bee àti àwọn ohun ìtàn tí ó ń fi ìdílé náà hàn pẹ́lú ipa tí wọ́n kò nínú òwò ẹrú
  • Ojú ọ̀nà Gbẹrẹfu náà jẹ́ ojú ọ̀ná kan tí ó lọ sí Point of No Return níbi tí àwọn ẹrú ọkùnrin àti obìnrin, ọmọdékùnrin àti ọmọdébìnrin tí wọn tó 500,000 níye tí wọ́n ti kò lèrú mo ń gbà lọ wọkọ̀ ojú-omi lọ sí ìlú òyìnbó.
  • Wọ́n ma ń fi tipá fún àwọn ẹrú ní omi inú kànga kan tí parí oògùn burúkú kan sí kí àwọn ẹrú ó má lè ba dojú ìjà kọ àwọn òyìnbó gẹ̀ẹ́sì tí wọ́n rà wọ́n, kí wọ́n má sì lè rántí ilé mọ́ láé.
  • Àwòrán ìdúná-dúrá lórí àwọn ẹrú tí wọ́n fẹ́ kó gba point of no return

Point of No Return ni ibi tí àwọn olówò-ẹrú ti ma ń dúná-dúrá ṣáájú kí wọ́n tó kò àwọn ẹrú wọkọ̀ ojú-omi.[11]

Àwọn itọ́ka sí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. Tijani, H.I. (2010). The African Diaspora: Historical Analysis, Poetic Verses, and Pedagogy. Learning Solutions. ISBN 978-0-558-49759-0. https://books.google.com.ng/books?id=fdFPAQAAIAAJ. Retrieved 2021-08-06. 
  2. A. Babatunde Olaide-Mesewaku (2001). Badagry district, 1863-1999. John West Publications Ltd.. ISBN 978-978-163-090-3. https://books.google.com/books?id=aJMuAQAAIAAJ. 
  3. Njoku. "Vlekete: When a slave market becomes a tourist centre". http://www.vanguardngr.com/2013/02/vlekete-when-a-slave-market-becomes-a-tourist-centre/. 
  4. "Back-To-Africa: A Dying Wish Births A Living Legacy". The Guardian Nigeria News - Nigeria and World News. 2020-02-09. Retrieved 2021-08-06. 
  5. Hakeem Ibikunle Tijani (2010). The African diaspora: historical analysis, poetic verses, and pedagogy. Learning Solutions. ISBN 978-0-558-49759-0. https://books.google.com/books?id=fdFPAQAAIAAJ. 
  6. A. Babatunde Olaide-Mesewaku; Babatunde A. Olaide-Mesewaku (2001). Badagry district, 1863-1999. John West Publications Ltd.. ISBN 978-978-163-090-3. https://books.google.com/books?id=aJMuAQAAIAAJ. 
  7. Njoku, Jude (6 February 2013). "Vlekete: When a slave market becomes a tourist centre". Vanguard Newspaper. http://www.vanguardngr.com/2013/02/vlekete-when-a-slave-market-becomes-a-tourist-centre/. Retrieved 16 January 2016. 
  8. "The dark history of the Nigerian colonial town of Badagry, one of Africa's first slave ports". Face2Face Africa (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2018-07-19. Retrieved 2021-08-19. 
  9. Bamidele, Michael (2020-02-09). "Back-To-Africa: A Dying Wish Births A Living Legacy". The Guardian Nigeria News - Nigeria and World News. Retrieved 2021-08-05. 
  10. Cite web|date=2014-01-18|title=Badagry and the remaining marks of slave market|url=https://www.vanguardngr.com/2014/01/badagry-remaining-marks-slave-market/%7Caccess-date=2021-08-19%7Cwebsite=Vanguard[Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́] News|language=en-US}}
  11. "Badagry Slave Route: Slaves passed these 5 notable stops on their journey of no return". Pulse Nigeria (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2021-07-26. Retrieved 2021-08-19. 

Àdàkọ:Lagos-stub Àdàkọ:Retail-market-stub