Jump to content

Bayo Ojo

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Christoper Adebayo Ojo
Federal Minister of Justice
In office
June 2005  May 2007
AsíwájúAkin Olujinmi
Arọ́pòMichael Aondoakaa
Àwọn àlàyé onítòhún
Ẹgbẹ́ olóṣèlúPeople's Democratic Party (Nigeria)
(Àwọn) olólùfẹ́Folashade
ProfessionLawyer

Christopher Adebayo Ojo, SAN fìgbà kan jẹ́ Attorney General ti orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.[1][2] Ó sì tún fìgbà kan jẹ́ olórí Nigerian Federal Ministry of Justice. Ó jẹ́ amòfin, ó sì láṣẹ láti ṣiṣẹ́ ní Nigeria, England àti Wales. Ó tún jẹ́ Senior Advocate of Nigeria.

Ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ ayé àti ẹ̀kọ́ rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ojo wá láti Ife-Ijumu, Kogi State,[3] ní Nigeria. Ó kẹ́kọ̀ọ́ alákòóbẹ̀rẹ̀ rẹ̀ ní Maiduguri àti Kaduna àti àwọn ẹ̀kọ́ ìyókù ní Zaria àti Kaduna State. Ó ṣiṣẹ́ fún ìgbà díẹ̀ ní Ilorin, Kwara State, kí ó tó lọ sí University of Lagos (in Lagos) níbi tí ó ti gboyè ẹ̀kọ́ nínú ìmọ̀ òfin ní June 1977. Ó fẹ́ He is Hon. Justice Folashade Bayo-Ojo, wọ́n sì jọ ní ọmọ méjì, Babatomiwa àti Olubusola. Ó ní àbúrò ọkùnrin méjì, Daniel Oluwasegun Ojo àti Victor Olanrewaju Ojo.

Ojo di agbẹjọ́rò ní July 1978. Ó ní ìṣàfihàn àkọ́kọ́ rẹ̀ ní ilé-ẹjọ́ lórí ọ̀rọ̀ ìfipábálòpọ̀ kan, níwájú Hon. Justice Anthony Iguh ti High Court of Justice, Enugu, ní ọdún 1978. Lásìkò náà, ó jẹ́ agùnbánirọ̀

Ó ṣiṣẹ́ ní Ministry of Justice, ní ìpínlẹ̀ Kwara, gẹ́gẹ́ bíi agbẹjọ́rò fún ìpínlẹ̀ náà fún ọdún mẹ́rin. Lásìkò yìí, ó gba ìwé-ẹ̀rí ní Royal Institute of Public Administration, ní London ní September, 1981. Lẹ́yìn náà, ó lọ sí London School of Economics and Political Science, University of London, láti gboyè LLM ní September 1982. Ní March 1983, ó fi iṣẹ́ ìjọba sílẹ̀ láti darapọ̀ mọ́ Oniyangi & Co gẹ́gẹ́ bíi olórí ilé-iṣẹ́ náà. Ní ọdún 1986, ó ṣèdásílẹ̀ ilé-iṣẹ́ tirẹ̀ tó pè ní Bayo Ojo & Co.

Wọ́n yàn án gẹ́gẹ́ bíi Nigeria Bar Association (NBA) ní ọdún 2004. Nígbà kan náà ni wọ́n yàn án sípò Attorney General àti Minister of Justice[4] láti ọwọ́ President Olusegun Obasanjo.

Ní ọdún 2007, ó di ọmọ-ẹgbẹ́ United Nations International Law Commission. Títí di òní, ó ń ṣiṣẹ́ pọ̀ pẹ̀lú Nasir EL-Rufai àti Nuhu Ribadu.

Àtòjọ àwọn iṣẹ́ rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. Mehler, Andreas; Melber, Henning; Walraven, Klaas Van (January 2007). Africa yearbook. BRILL. pp. 158–. ISBN 978-90-04-16263-1. https://books.google.com/books?id=VEqZ8rep_A0C&pg=PA158. Retrieved 9 May 2011.
  2. Ojakaminor, Efeturi (2007). Aso Rock and the arrogance of power. Ambassador Publications. p. 272. https://books.google.com/books?id=srIuAQAAIAAJ. Retrieved 9 May 2011.
  3. "Group backs Bayo Ojo for minister". Vanguard News (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2015-09-30. Retrieved 2022-03-03.
  4. Tucker, Andrew (2009-01-02). Queer visibilities: space, identity and interaction in Cape Town. Wiley-Blackwell. pp. 206–. ISBN 978-1-4051-8302-4. https://books.google.com/books?id=XQZJ1zGK8-oC&pg=PA206. Retrieved 9 May 2011.
  5. https://www.pressreader.com/nigeria/thisday/20190326/281895889590691. Retrieved 2020-01-10 via PressReader. Missing or empty |title= (help)