Ọlátóyè Tèmítọ́pẹ́ Sugar
Olatoye Temitope Sugar | |
|---|---|
| Member of the House of Representatives of Nigeria for Lagelu/Akinyele | |
| In office 9 June 2015 – 9 March 2019 | |
| Asíwájú | Muritala Kayode Adewale |
| Àwọn àlàyé onítòhún | |
| Ọjọ́ìbí | 1973 |
| Aláìsí | 9 March 2019 (ọmọ ọdún 45–46)[1] Ibadan, Oyo State, Nigeria |
| Ọmọorílẹ̀-èdè | Nigerian |
| Ẹgbẹ́ olóṣèlú | Action Democratic Party |
| Alma mater |
|
| Occupation |
|
| Website | http://olatoyetemitopesugar.com |
Ọlátóyè Tèmítọ́pẹ́ Sugar tí a bí ní ọdún 1973 ó jáde làyé ní ọjọ́ kẹsàn-án Oṣù Kẹta ọdún 2019) jẹ́ ọmọ Ilé ìgbìmọ̀ Aṣojú ṣòfin ìjọba Àpapọ̀ tí ó ń ṣojú fún agbègbè Lagelu / Akinyele, àti alága Ilé lórí Ìdàgbàsókè àwọn Ìlú àti Ètò Agbègbè fún Orílẹ̀-èdè Nàìjíría . [2] Ó tún jẹ́ olùdíje sílé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà fún àrin gbùngbùn ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ lábẹ́ àsìà ẹgbẹ́ òṣèlú Action Democratic Party nínú ìdìbò ọdún 2019.
Ìgbésí ayé rẹ̀ àti ilé ẹ́kọ̀ tó lọ
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Sugar wá láti agboolé Ẹfúngadé-Onígbòdògì, Aláfárá Òjé ní ìjọba ìbílẹ̀ Àríwá-Ìlà oòrùn Ìbàdàn ní Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́, nígbà tí àwọn baba ńlá rẹ̀ jẹ́ Onígbòdògì àti Àlàpẹ́ tí àwọn méjèèjì wà ní ìjọba ìbílẹ̀ Lagelu ní ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́. Nígbà tí ó wà ní èwe, Tèmítọ́pẹ́ kẹ́kọ̀ọ́ ní ilé ìwé alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ Máíkẹ̀lì mímọ́ tí ó wà ní agbègbè, Yemetu àti ilé ìwé alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ IMG tó wà ní agbègbè Bẹ́yẹrúnkà, Aláfárá Òjé ní ìlú Ìbàdàn. Lẹ́yìn náà ó tẹ̀síwájú sí Ilé ìwé oníwèé mẹ́wàá ti Ìkọ́làbà, kọ́lẹ́ẹ̀ji ti Lúkù mímọ́ ní Mọ̀lété àti Ilé ìwé oníwèé mẹ́wàá Alugbó to wà ní, Ẹgbẹ́dá, gbogbo àwọn ilé ẹ̀kọ́ yìí wà ní ìlú Ìbàdàn, Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́, gbogbo wọn lósì lọ fún ẹ̀kọ́ girama rẹ̀. [3] Lẹ́yìn náà, ó lọ sí Kọ́lẹ̀jì ìjọba àpapọ̀ tó wà ní Abeokuta, Ìpínlẹ̀ Ogun, níbi tí ó ti gba ìwé ẹ̀rí olùkọ́ni. Lẹ́yìn náà, ó lọ sí Yunifásítì Ibadan níbi tí ó ti kẹ́kọ̀ọ́ gboyè ìmọ̀ ìjìnlẹ àkọ́kọ́ àti ìkejì. [4]
Gẹ́gẹ́ bí olòṣèlú
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Iṣẹ́ òṣèlú Sugar bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú yíyàn sípò gẹ́gẹ́ bí alábojútó ní ìjọba ìbílẹ̀ Ọdẹ́dá . Lẹ́yìn náà ni wọ́n yàn án gẹ́gẹ́ bí olùdámọ̀ràn pàtàkì ní ìpínlẹ̀ ní ìpínlẹ̀ Ogun lábẹ́ ìṣàkóso gómìnà, Ọ̀túnba Gbenga Daniel, nítorí pé ó jẹ́ olórí àwọn ọ̀dọ́ fùn ẹgbẹ́ òṣèlú PDP ní agbègbè ààrin gbùngbùn ìpínlẹ̀ Ògùn fún ọ̀pọ̀ ọdún. Ó díje fún ipò alága ìjọba ìbílẹ̀ Lagelu ní ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ní ọdún 2007 lábẹ́ àsià ẹgbẹ́ òṣèlú People's Democratic Party (PDP) ó sì di aṣojú ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ fún ẹgbẹ́ òṣèlú PDP ní ọdún 2008.
Wọ́n dìbò yan Sugar sí Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ní ọdún 2011 níbi tí wọ́n ti dìbò yàn án lábẹ́ àsìá ẹgbẹ́ òṣèlú accord [5] àti ní ọdún 2015, ó díje fún ipò aṣojú ṣòfin láti ṣojú fún ẹkùn Lágelú/Akínyẹlé lábẹ́ àsìá ẹgbẹ́ òṣèlú ti All Progressive Congress (APC) tí ó sì jáwé olúborí. Ní ọdún 2018, Sugar lọ sínú ẹgbẹ́ òṣèlú ti Action Democratic Party ó sì díje fún ipò Aṣòfin àgbà tí ó ń ṣojú fún agbègbè àárín gbùngbùn ìpínlẹ̀ Ọyọ́. Ó pàdánù ìdìbò náà sọ́wọ́ Teslim Folarin, olùdíje láti inú ẹgbẹ́ òṣèlú ti APC.
Ikú
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Wọ́n yìnbọn fún Sugar ní Lálúpọn ní ọjọ́ kẹsàn-án oṣù kẹta ọdún 2019. Wọ́n yára gbé e lọ sí ilé ìwòsàn University College, Ìbàdàn níbi tí ó kú sí látàrí ọgbẹ́ tí ó ní látara ìbọn tí wọ́n yìn fun. [6] [7]