Jump to content

Babatunde Fashola

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
His Excellency

Babatunde Raji Fashola

SAN
Minister of Works and Housing
Lọ́wọ́lọ́wọ́
Ó gun orí àga
11 November 2015
ÀàrẹMuhammadu Buhari
13th Gómìnà Ìpínlẹ̀ Èkó
In office
May 29, 2007  May 29,2015
AsíwájúBola Tinubu
Arọ́pòAkinwunmi Ambode
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí28 Oṣù Kẹfà 1963 (1963-06-28) (ọmọ ọdún 62)[1]
Lagos State, Nigeria
Ẹgbẹ́ olóṣèlúAll Progressive Congress
(Àwọn) olólùfẹ́Abimbola Emmanuela Fashola
Occupationlawyer, Politician

Babatunde Raji Fashola (tí a bí ní 28 June, 1963) jẹ́ agbẹjọ́rò àti olóṣèlú órílẹ̀-èdè Nàìjíríà.[2] Ó ti fìgbà kan jẹ́ Gómìnà Ìpínlẹ̀ Èkó fún sáà méjì láti ọdún 2007 sí ọdún 2015 lábẹ́ àsíá ẹgbẹ́-òṣèlú All Progressives Congress. Olóyè Bola Tinubu ni ó jẹ́ Gómìnà Ìpínlẹ̀ Èkó ṣáájú rẹ̀.[3][4] Lodun 2015, Ààrẹ Muhammadu Buhari yàn-án gẹ́gẹ́ bí Mínísítà fún ètò iná-mọ̀nàmọ́ná, ilé ìgbé, àti iṣẹ́. Ààrẹ tún tún-un yàn lọ́dún 2019 sí ipò yìí kan náàsí ipò Mínísítà fún Agbára àti ìná mọ̀nàmọ́ná.[5]

Ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ ayé rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bí Fashola ní ọjọ́ 28 June, ọdún 1963,[6]Ìpínlẹ̀ Èkó, ní Island Maternity Hospital, sínú ìdílé Ademola Fashola, tó fìgbà kan jẹ́ akọ̀ròyìn fún ìwé-ìròyìn Daily Times ti Nàìjíríà, àti Olufunke Agunbiade, to jẹ́ nọ́ọ̀sì.[7]

Iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bíi Amòfin

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ilé-ẹjọ́ gíga

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́n pè é sí ilé-ẹjọ́ gẹ́gẹ́ bíi agbẹjọ́rò àti onídùúró ti ilé-ẹjọ́ gíga ní November 1988[8] lẹ́yìn tó kẹ́kọ̀ọ́ gboyè ní Nigerian Law School, ní ìpínlẹ̀ Èkó láàárín ọdún 1987 àti 1988.[9]

Àmi-ẹ̀yẹ rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Fashola, tó jẹ́ ènìyàn kan tó gbajúmọ̀ ní Ilé-ẹjọ́ Gígajùlọ ilẹ̀ Nàìjíríà, ti gba àmì-ẹ̀yẹ àti ìwé-ẹ̀rí títayọ bíi Distinguished Alumnus Award tí ìgbìmọ̀ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ gboyè ti Yunifásítì ìlú Benin fún un.[10] Ó tún gba àmì-ẹ̀ye ti Lagos State public service club Platinum Award fún iṣẹ́ títayọ rẹ̀ sí ìdàgbàsókè. Bẹ́ẹ̀ náà ni ti Alliance for Democracy, "àmì-ẹ̀yẹ ti ìjọba ìbílẹ̀ Igbogbo Bayeku" ní ìbámu pẹ̀lú ìfarahàn àti iṣẹ́ rẹ̀ sí ẹgbẹ́ náà.

Babatunde Fashola tún jẹ́ alábòójútó àwọn akẹ́kọ̀ó ìmọ̀-òfin, tí Yunifásítì ìlú Benin, òun sì ni akẹ́kọ̀ọ́ kejì tó máa kẹ́kọ̀ọ́ nípa ìmọ̀-òfin ní Yunifásítì ìlú Benin, àti ọmọ ẹgbé Nigerian Law School àkọ́kọ́ tó kẹ́kọ̀ọ́ gboyè ní ọdún 1988, tí wọ́n fi joyè Senior Advocate of Nigeria.[11] Fashola náà ni Chief of Staff àkọ́kọ́ tó gba irú oyè bẹ́è. Babatunde Fashola jẹ́ ọmọ-ẹgbẹ́ Nigerian Bar Association, International Bar Association àti Chartered Institute of Taxation of Nigeria.

Ní oṣù kẹwàá ọdún 2022, oyè ńlá tí orílẹ̀-èdè Nàìjíríà kan tí a mọ̀ sí oyè Commander of the Order of the Niger (CON) ni a tún fi dá a lọ́lá láti ọwọ́ Ààrẹ Muhammadu Buhari.[12]

Àwọn Ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. "HIS EXCELLENCY, BABATUNDE RAJI FASHOLA (SAN), GOVERNOR OF LAGOS STATE, NIGERIA". Commonwealth Business Council. Archived from the original on 2010-07-22. Retrieved 2010-02-14.
  2. "Governor Babatunde Raji Fashola - Profile". Africa Confidential. 2019-10-03. Retrieved 2019-10-03.
  3. "His Excellency Mr. Babatunde Raji Fashola, SAN". lagosstate.gov.ng Lagos State Government. Archived from the original on 10 December 2009. Retrieved 27 January 2010. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  4. "FG, agencies to construct 1,800km road at N621b". The Guardian Nigeria News - Nigeria and World News (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2021-12-22. Archived from the original on 2022-02-22. Retrieved 2022-02-22.
  5. Toromade, Samson (2019-08-21). "Fashola loses Power ministry, retains Works and Housing". Google. Archived from the original on 2019-09-13. Retrieved 2019-10-03.
  6. John M. O. Ekundayo (2013). Out of Africa: Fashola: Reinventing Servant Leadership to Engender Nigeria's Transformation. AuthorHouse. p. 18. ISBN 978-1-481-7904-06. https://books.google.com/books?id=WjhKyg8OjBUC&q=fashola+yoruba&pg=PA18.
  7. "Babatunde Fashola biography, net worth, age, family, contact & picture". www.manpower.com.ng. Retrieved 2022-01-18.
  8. "Ministerial nominee, Babatunde Raji Fashola's CV". Vanguard News (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2015-10-12. Retrieved 2022-02-28.
  9. Ajumobi, Kemi (2015-07-05). "Babatunde Raji Fashola, the irrefutably astounding transformational leader". Businessday NG (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2020-06-04.
  10. Àṣìṣe ìtọ́kasí: Invalid <ref> tag; no text was provided for refs named :12
  11. Lagos State Government. "Babatunde Raji Fashola (2007 – 2015)". Archived from the original on 2023-03-02. Retrieved 2023-03-02.
  12. "FULL LIST: 2022 National Honours Award Recipients The Nation Newspaper" (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2022-10-09. Retrieved 2022-10-31.