Jump to content

Lateef Jakande

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Lateef Kayode Jakande
Governor of Lagos State
In office
October 1979  December 1983
AsíwájúEbitu Ukiwe
Arọ́pòGbolahan Mudasiru
Minister of Works
In office
November 1993  August 1998
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí23 Oṣù Keje 1929 (1929-07-23) (ọmọ ọdún 96)
Lagos Island, Lagos, Lagos State, Nigeria
OccupationJournalist

Lateef Káyọ̀dé Jakande ẹni tí a bí ní ọjọ́ kẹtàlélógún, oṣù keje, ọdún 1929 tí ó sì dágbére fáyé ní ọdún 2021 (23 July 1929-2021). Ó jẹ́ ọmọ bíbí orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tí ó sì ti fi ìgbà kan rí jẹ́ GómìnàÌpínlẹ̀ Èkó ati alákòóso ètò iṣẹ́ abẹ́lé lábẹ́ ìjọba ológun ọ̀gágun Sani Abacha.[1][2]

Ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ayé rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bí Lateef Káyọ̀dé Jakande ní agbègbè Epetedo ní Erékùṣù Èkó, ní Ìpínlẹ̀ Èkó ní ọjọ́ kẹtàlélógún, oṣù Keje, ọdún 1929. Àwọn òbí rẹ̀ méjéèjì wá láti ìlú Òmù-Àrán ní Ìpínlẹ̀ Kwara . Ó lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ ní Ilé-ẹ̀kó gbogbogboò ti Èkó ní Ẹnu-Ọwá, èyí tí ó wà ní Erékùsù ìlú Èkó, lẹ́yìn náà ni ó lọ sí Bunham Memorial Methodist School, Port Harcourt láàárín ọdún 1934 sí ọdún 1943. Ó kẹ́kọ̀ọ́ jáde ní King's College, Èkó ní ọdún 1943, lẹ́yìn náà ni ó lọ sí Ilé-ẹ̀kọ́ girama ní Iléṣà ní ọdún 1945, níbi tí ó ti ṣe àtúnṣe sí ìwé kan tí à ń pè ní The Quarterly Mirror.

Ní ọdún 1949, Jakande bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìròyìn ní àkọ́kọ́ pẹ̀lú ilé-iṣẹ́ Daily Service, lẹ́yìn náà ní ọdún 1953 ó dara pọ̀ mọ́ ilé-iṣẹ́ ìròyìn Nigerian Tribune. Ní ọdún 1956, Olóyè Obafemi Awolowo, ẹni tí ó ní ilé-iṣẹ́ ìwé ìròyìn yìí yàn án gẹ́gẹ́ bí olóòtú àgbà[3] ti ilé-iṣẹ́ ìwé ìròyìn Nigerian Tribune.

Lẹ́yìn tí Jakande kúrò ní Tribune ní ọdún 1975, ó dá ìwé ìròyìn John West Publications sílẹ̀, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í tẹ ìwé ìròyìn Ìròyìn Èkó (The Lagos News) jáde. Ó jẹ gẹ́gẹ́ bíi ààrẹ àkọ́kọ́ ti Newspaper Proprietors Association of Nigeria (NPAN).

Ìṣàkóso rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Gómìnà Ìpínlẹ̀ Èkó

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]


Iṣẹ́ tí ó ṣe lẹ́yìn tí ó kúrò nípò Gómìnà Ìpínlẹ̀ Èkó

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]


Lẹ́yìn ìgbésí-ayé àti ikú rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Lateef Jakande papòdà ní ìlú Èkó ní ọjọ́ kọkànlá, oṣù kejì, ọdún [4]. Wọ́n sin òkú rẹ̀ sí Vaults and Gardens Cemetery, ní ìlú Ìkóyì, ìpínlẹ̀ Èkó ní ọjọ́ Ẹtì, ọjọ́ kejìlá, oṣù kejì, ọdún 2021. Ó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ará ìlú Èkó mẹ́rin tí wọ́n jẹ́ ọmọ Yorùbá tí wọ́n ṣe ayẹyẹ ỌDÚN Ẹ̀YỌ̀ èyí tí wọ́n ṣe ní ọjọ́ kẹtàdínlógún, oṣù kejì, ọdún 2025 fún ipa tí ó kó nínú ìdàgbàsókè ìlú Èkó gẹ́gẹ́ bíi Gómìnà.

Lateef Jakande jẹ́ àjèjì láàárín àwọn gbajúmọ̀ ìlú Èkó nítorí pé ìdílé rẹ̀ ò wá láti Erékùṣù ìlú Èkó ṣùgbọ́n wọ́n wá láti ìpínlẹ̀ Kwara. Bẹ́ẹ̀ ní ó tún jẹ́ ìgbà àkọ́kọ́ tí wọn ó bu ọlá fún ẹni tí kì í ṣe ọmọ bíbí ìlú Èkó, ẹni tí í ṣe Sir Michael Ọ̀tẹ́dọlá tí ó jẹ́ ọmọ bíbí Yorùbá Ẹ̀pẹ́. Arábìnrin Tinubu àti Olóyè Abibatu Mọ́gàjí nìkan ni wọ́n wá láti ìdílé tí wọ́n wá láti ààrin gbùngbùn Erékùṣù Èkó. Òǹkọrin ọmọ Yorùbá ẹni tí í ṣe K1 De Ultimate kọ orin kan fún un láti bu ọlá rẹ̀ ní ọdún 2013.

Ẹni ẹ̀kẹrin tí ó gbajúmọ̀ tí wọ́n tún bu ọlá fún ni Brigadier-General Mobolaji Olufunsho Johnson ẹni tí ó jẹ́ ọmọ bíbí ilẹ̀ Èkó. Ṣùgbọ́n tí ó wá láti ẹ̀yà Saro ní ìlú Èkó nítòsí Marina. Ó jẹ́ ọmọ bíbí Joshua Motola Johnson àti ìyàwó rẹ̀, Gbémisọlá Johnson (née Dudley-Coker) ni.

Ó jẹ́ àǹfààní tuntun lẹ́yìn ọdún mẹ́jọ láìsí ọdún Ẹ̀yọ̀ ní ìlú Èkó, lẹ́yìn tí ó jẹ́ pé àwọn olórí tí wọ́n gbajúmọ̀ tí wọ́n máa ń bu ọlá fún tẹ́lẹ̀ jẹ́ àwọn tí wọ́n wá láti Eko-Lagos nìkan, fún Gómìnà ACN láti kó gbogbo àwọn ará ìlú Èkó jọ láti wà ní ìdánimọ̀ kan ṣoṣo tí ó gbòòrò ju ti ìdánimọ̀ Yorùbá Èkó lọ, ṣùgbọ́n tí ó ṣe pàtàkì fún gbogbo àwọn ará ìpínlẹ̀ Èkó, láti Badagry (Ìwọ̀-oòrùn) dé Ẹ̀pẹ́ (ìlà-oòrùn) pẹ̀lú Ìkòròdú. Ó bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú Ẹ̀yọ̀ fún NCNC TOS Benson àti pé nísinsìnyí pẹ̀lú Gómìnà ológun àkọ́kọ́ ti ìpínlẹ̀ Èkó, Mobolaji Olufunsho Johnson.

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. Lai Olurode (21 July 2009). "Lateef Jakande at 80". The Guardian. UK. Archived from the original on 15 February 2022. Retrieved 23 December 2009. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  2. "His Excellency Alhaji Lateef Kayaode Jakande, Governor of Lagos State". Library of Congress Pamphlet Collection - Flickr. 2 May 2014. Retrieved 11 May 2014.
  3. "10 Quick Facts About Former Lagos Governor Lateef Jakande". The Guardian Nigeria News - Nigeria and World News (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2021-02-11. Retrieved 2022-03-07.
  4. "Late Lateef Jakande buried in Lagos". Vanguard News (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2021-02-12. Retrieved 2021-03-03.