Jump to content

Adeyinka Adebayo

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
(Àtúnjúwe láti Robert Adeyinka Adebayo)
Major General Robert Adeyinka Adebayo
Fáìlì:Photo of late Gen. Robert Adeyinka Adebayo.jpg
Chief of staff Army headquarters
In office
February 1964  November 15, 1965
AsíwájúFirst indigenous Chief of Staff of the Nigerian Army
Arọ́pòLate Colonel Kur Mohammed[1]
Governor Western Region/State
In office
Aug 4th 1966  April 1971
AsíwájúLate Col. Francis Adekunle Fajuyi[2]
Arọ́pòBrig. Oluwole Rotimi
Commandant of the Nigerian Defence Academy[3]
In office
1971–1972
LieutenantNull
AsíwájúBrigadier General D. A. Ejoor
Arọ́pòMajor General EO Ekpo
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí(1928-03-09)Oṣù Kẹta 9, 1928
Iyin Ekiti, Ekiti State
Ọmọorílẹ̀-èdèNigerian
Ẹgbẹ́ olóṣèlúOne of the founders of/Vice Chairman of the National Party of Nigeria (NPN) (1979 -1983), Alliance for Democracy
Alma materStaff College, Camberley, Imperial Defence College, London
OccupationSoldier/Government/Politics

Robert Adeyinka Adebayo (ti a bí ní ọjọ́ kẹsán Oṣù Kẹta ọdún 1928 – kú ní ọjọ kẹjọ Oṣù Kẹta ọdún 2017) jẹ́ ọ̀gágun àgbà (Major General) ní ọmọ ogun ilẹ̀ Nàìjíríà tí ó ṣèrànwọ́ gẹ́gẹ́ bí gomina ti ìpínlẹ̀ ìwọ̀orùn orílẹ-èdè Nàìjíríà tí wọ́n ti fopin sí ní báyìí, láàárín ọdún 1966–1971.[4] Ó tún jẹ́ olóyè asíwájú àwọn oṣiṣẹ (Chief of Staff) ní ọmọ ogun ilẹ̀ Nàìjíríà, ó sì jẹ́ apàṣẹ (Commandant) ti Nigerian Defence Academy.

Ìbẹ̀rẹ̀ ìgbésí ayé

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Adeyinka Adebayo ni wọ́n bí ní ọdún 1928, ọmọ oṣiṣẹ́ Public Works láti Iyin Ekiti, lẹ́gbẹ̀ẹ́ Ado Ekiti (ní ìpínlẹ̀ Ekiti báyìí), Nàìjíríà. Ó kàwé ní All Saints School, Iyin-Ekiti, ó sì tẹ̀síwájú sí Eko Boys' High School àti Christ’s School, Ado Ekiti.

Ó darapọ̀ mọ́ West African Frontier Force ní ọdún 1948 gẹ́gẹ́ bí regiment signaller, ó sì parí Officer Cadet Training Course ní Teshie, Ghana láti ọdún 1950 sí 1952. Lẹ́yìn tí ó yege níbi ìdánwò War Office fún àwọn cadet Commonwealth ní ọdún 1952 àti ìdánwò West African qualifying ní ọdún 1953, wọ́n yàn án gẹ́gẹ́ bí ọ̀físa ní Royal West African Frontier Force (RWAFF), gẹ́gẹ́ bí ọ̀físa ọmọ-ogun West Africa tí ó jẹ́ kẹtàlélogún (WA23), àti gẹ́gẹ́ bí ọ̀físa ọmọ-ogun Nàìjíríà tí ó jẹ́ ẹlẹ́keje (N7) lẹ́yìn tí ó parí War Office Cadet Training ní Eaton Hall, England. Ó tún lọ sí Staff College course ní Camberley, Surrey ní ọdún 1960, lẹ́yìn náà o sì lọ sí Imperial Defence College, ní ìlú London ní ọdún 1965, nínú èyí tí ó jẹ́ ọ̀kàn ṣoṣo lára àwọn ọ̀físa Áfíríkà tí o wà níbẹ̀.

Adeyinka Adebayo di ọ̀físa ní ọdún 1953. Àwọn ipò gbóògì lẹ́nu iṣẹ rẹ̀ ni wọnyi:

  • Platoon Commander, ọdún 1954–1955
  • Regimental Signal Officer, ọdún 1955–1957
  • Láàrin ọdún 1957–1958: o jẹ́ Aide-de-camp fún Gómìnà-Gẹ̀ẹ́sì (Gómìnà-Gẹ̀ẹ́sì ìkẹyìn fún Nàìjíríà ṣáájú òmìnira— Sir James Robertson, ní ọdún 1957)[5]
  • Company àti Detachment Commander, Ikoyi, ní ọdún 1958–1960
  • Ọ̀gágun ófísà fún ẹka làákàyè tí ó jẹ́ ọmọ Nàìjíríà àkọ́kọ́ ní UN, ní ọdún 1961
  • Ọ̀gágun ófísà àkọ́kọ́, ní kílásì kejì (Grade 2) ní Nigerian Army Headquarters, ọdún 1961–1962
  • Ọ̀gágun ófísà orílẹ-èdè Nàìjíríà àkọ́kọ́, ní kílásì àkọ́kọ́ (Grade 1), ní ọdún 1962–1963
  • Apàṣẹ ológun (Commander), Nigerian contingent ní Congo, ní ọdún 1963
  • Ó ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí ófísà (staff officer) ní ìdá àlàáfíà padà sílu (UN peacekeeping) ní ọ̀rọ̀ ogun Congo ní ọdún 1961–1963
  • Olóyè fún gbogbo òṣìṣẹ́ (Chief of Staff) fún àwọn ọmọ ogun orílẹ-èdè Nàìjíríà, ní oṣù kejì ọdún 1964 – oṣù kọkànlá ọdún 1965 (àkọ́kọ́ ọmọ Nàìjíríà tí yóò jẹ́ olóyè fún gbogbo òṣìṣẹ́ (Chief of Staff).
  • Alága, OAU Defence Planning Committee, ọdún 1963–1965
  • Olórí àwọn aṣojú ọmọ orílẹ-èdè Nàìjíríà sí ìpéjọ OAU ní Ethiopia, oṣù kọkànlá ọdún 1966.
  • Gómìnà ológun, ẹka ìwọòrùn Nàìjíríà, ní ọdún 1966–1971.
  • Apàṣe ológun (Commandant), fún Nigerian Defence Academy, ní ọdún 1971–1972.
  • Adarí ètò ayẹyẹ àwọn ọmọ ológun (Ceremonial military duties), ní ọdún 1972–1975.
  • Ó fẹ̀yìntì kúrò nínú iṣẹ́ ọmọ ológun pẹ̀lú ipò Ọ̀gágun Àgbà (Major General) ní oṣù keje ọdún 1975.
  • Ọkan lára àwọn olùdásílẹ̀ àti igbákejì alága ti ẹgbẹ òṣèlú National Party of Nigeria (NPN), láti ọdún 1979–1983.

Gómìnà iwọ̀-òrùn orílẹ-èdè Nàìjíríà

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Gẹ́gẹ́bí Gómìnà iwọ̀-òrùn orílẹ-èdè Nàìjíríà, ó ṣe àtìlẹ́yìn fún ètò ìlọsíwájú oun ọ̀gbìn, pàápàá jùlọ ní ìdásílẹ̀ Ilé-ìwé ṣiṣe àwárí àwọn ǹkan ọ̀gbìn (Institute of Agricultural Research and Training, Moor Plantation), ní ìlú Ibadan.[6]

Ogun Biafra

Adebayo gbà wọn ní ìmọràn pé kí wọ́n má fipá dá ogun Biafra dúró. Ní ọ̀rọ̀ tó mọ́ ọn kedere gan-an, ó sọ pé:

Miò nilò láti sọ fún yín nípa ìbànújẹ, ìparun àti ìjìyà ọmọnìyàn tí lílo agbára ogun yóò mú bá wa. Nígbà tí gbogbo rẹ̀ bá parí, tí erù àti erupẹ̀ bá balẹ̀, tí wọ́n bá sì sin àwọn tí ó kú, a ó rí i pé bí àwọn míìràn náà o ṣe rí i, pé gbogbo rẹ̀ kì í ṣe ìfipámúni, kò sì ní yanju iṣoro tí a fẹ́ yanjú.[7]

Ní ìbẹ̀rẹ̀ ogun, Colonel Adebayo, gómìnà ìpínlẹ̀ iwọ̀-orùn nígbà yẹn, paṣẹ kí wọ́n wó gbogbo afárá tí o wọlé sí ìpínlẹ̀ iwọ̀-orùn kí àwọn ọmọ-ogun Biafra má ba lè dé Eko, tínse olú-ìlú Nàìjíríà nígbàyen. Wọ́n dé Ore tin bẹ ní ìpínlẹ̀ Ondo lonii, bíi kìlómítà ọgọ́run sí Èkó.

Lẹ́yìn ogun náà, Olórí orílẹ-èdè Nàìjíríà nígbà náà Ọ̀gágun Yakubu Gowon yàn án gẹ́gẹ́ bí alága ti aàjọ tin mójútó ìdá àlàáfíà padà sílu àti fífi àwọn igbo (Biafrans) padà sínú Nàìjíríà.

Ìdìtẹ̀ àwọn àgbẹ̀

Ọ̀gágun àgbà Adebayo ni ó jẹ́ Gómìnà nígbà ìdìtẹ̀ àwọn ẹgbẹ́ “Agbekoya” lórí owó orí sísan àwọn àgbẹ̀, èyí tí wọ́n padà yanjú ní àlàáfíà. Robert Adeyinka Adebayo fẹ̀yìntì kúrò ní ẹnu ìṣẹ́ ọmọ-ológun ní ipò Ọ̀gágun Àgbà (Major General) ní ọdún 1975.

Ìgbésí Ayé Lẹ́yìn Iṣẹ́ Ológun

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní ọdún 2011, Adebayo jẹ́ alága ìgbìmọ̀ àgbà àwọn yorùbá[8]. Àkọ́bí rẹ̀, Otunba Niyi Adebayo, jẹ Gómìnà ìpínlẹ̀ Ekiti láti ọdún 1999 sí 2003. Ọmọ rẹ̀ míìràn, Adedayo Adebayo, jẹ́ agbábọọlu rugby fún Bath àti ẹgbẹ́ agbáabọ̀lù orílẹ-èdè England láàárín ọdún 1996 sí 1999, níbi tí ó ti gba àmì ẹ̀yẹ àgbáyé mẹfa (six international caps).

ọjọ́ kan sí ọjọ ìbí kọkàndínlàadọ́run (89th birthday) rẹ̀, Adebayo kú ní ọjọ́ kẹjọ oṣù kẹta ọdún 2017, ní ilé ìgbé rẹ̀ ní Èkó[9].