Ọba ìlú Èkó

Ọba ìlú Èkó ni atáyéṣe átọwọ́dọ́wọ́ olórí ìlú Èkó ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Ọba ìlú Èkó lọ́wọ́lọ́wọ́ ní Ọba Rilwan Akiolu tó dípò Ọba Adeyinka Oyekan kejì tó ṣe aláìsí ní ọdún 2003.
Ọba jẹ́ aláṣẹ ìlú Yorùbá, alákóso ìṣe-àṣà (ceremonial) tí kò ní agbára ìṣèlú taara, ṣùgbọ́n àwọn olóṣèlú máa ń tọ̀ ọ́ wá gẹ́gẹ́ bí alábàágbékalẹ̀ tàbí olùrànlọ́wọ́ nígbà tí wọ́n bá ń wá àtìlẹ́yìn lọ́dọ̀ ará Èkó, ilú tí ó jẹ́ ọkàn owó ní Nàìjíríà àti ìlú tó tóbi jùlọ ní Áfíríkà. Ọba ti farahàn nínú àwọn ìpolówó ìrìnàjò (tourism) fún ìlú náà, níbi tí ó ti máa ń sọ pé, “Ẹ gbọ́dọ̀ lọ sí Èkó” (“You’ve gotta go to Lagos”), pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ipa ìṣe-àṣà míìràn.
Ìtàn
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Gbogbo àwọn Ọba Èkó ń tọ́pa ìpìlẹ̀ ìran wọn padà sí Ashipa-ọmọ Awori kan[1], olórí ogun fún Ọba Benin. A fun Ashipa ní oyè Olórí ogun[2] a sì fún un ní àṣẹ láti ṣàkóso Èkó ní orúkọ Ọba Benin.[3][4]Ashipa gba idà àti ìlù ọba gẹ́gẹ́ bí ààmì àṣẹ rẹ̀ lọ́wọ́ Ọba Benin nígbà tí a rán án sí Èkó. Pẹ̀lú èyí, Ọba Benin tún rán ẹgbẹ́ àwọn olórí Benin kan wá láti bójú tó ànfàní Benin ní Èkó. Àwọn olórí wọ̀nyí, tí Ẹlẹ́tù Odibo ń darí, ni wọ́n jẹ́ ọmọ ìbẹ̀rẹ̀ ìpele Akarigbere nínú àwọn Oloye Ìbòrí Funfun (White Cap Chiefs) ti Èkó.[2] Kí ìjọba Gẹ̀ẹ́sì tó dé, Ọba Benin ní “ẹ̀tọ́ tí kò sí ẹni tó lè tako láti fi adé lé ẹni tí àwọn ará Èkó bá yàn gẹ́gẹ́ bí Ọba wọn[5].
Ìsákọ́lẹ̀ (owó-orí/ẹ̀bùn) ń lọ láti Erékùsù Èkó sí Benin fún ọ̀pọ̀ ọdún títí di ǹkan bi ọdún 1830 nígbà tí Èkó dá a dúró. Ní àkókò yìí, ipo Èkó gẹ́gẹ́ bí agbára olómìnira tirẹ̀ ti gòkè gidigidi, ó sì ti lágbára tó bẹ́ẹ̀ tí kò rọrùn láti kolu. Fún ìdí èyí, Ọba Benin gbọ́dọ̀ ní ìtẹ́lọ́rùn pẹ̀lú ẹ̀bùn àìpẹ́pẹ́ tí kò jẹ́ ìsákọ́lẹ̀ dandan mọ́, ṣùgbọ́n ẹ̀bùn ìrántí ìtàn ni.[6]
Ìṣẹ́gun àwọn ọmọ ogun Gẹ̀ẹ́sì lórí Ọba Kosoko ní ọjọ́ kejìdínlọ́gbọ̀n Oṣù Kejìlá ọdún 1851, ní ìṣẹ̀lẹ̀ tí a mọ̀ sí ìkolù ìlú Èkó (Bombardment of Lagos) tàbí àdínkù ìlú Èkó (Reduction of Lagos), tàbí ní èdè abínibí gẹ́gẹ́ bí Ogun Ahoyaya tàbí Ogun Agidingbi (èyí tí ó túmọ̀ sí “nkan ogun tí o gbóná”) fi òpin sí gbogbo irú ìsákọ́lẹ̀ (ẹ̀bùn tàbí ìjẹ̀nípá) àti ìbáṣepọ̀ Èkó sí Ọba Benin.[7]
Nítorí náà, Kosoko ni Ọba Èkó ìkẹyìn tí ó kópa nínú ẹ̀bùn ìrántí láti ọdọ́ ará Èkó sí Ọba Benin. Ọba Akitoye, ẹni tí àwọn Gẹ̀ẹ́sì tún fi jókòó lórí itẹ́, “lo àǹfààní ìpadàbọ̀ rẹ̀ lábẹ́ ààbò Gẹ̀ẹ́sì láti kọ ìgbọ́ràn àtijọ́ rẹ̀ sí Benin,” ó sì kọ gbogbo ìbéèrè ìsákọ́lẹ̀ tí Ọba Benin n bèrè fún.[8][9][10].
Àwọn Ọba Èkó tí o jẹ ṣáájú ti lo àwọn orúkọ oyè Ológun (tí ó wá láti ara Olórí ogun), Eléko, àti ní àkókò tuntun jùlọ, Ọba Èkó.[11]
Ìtẹ́ Ọba
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ilé ìjẹ Ọba, láti ọdún 1630, ni Iga Idunganran, àgọ́-ọba kan tí àwọn Pọtúgí ṣe àtúnṣe rẹ̀ lọ́pọ̀lọpọ̀ ọdún, tó fẹrẹ̀ tó ọgọ́rùn-ún ọdún.[12] Lónìí, ó jẹ́ ibi ìrìnàjò olókìkí gan-an
Àtòjọ àwọn Ọba ìlú Èkó
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Ashipa (c1682-1716)
- Ọba Ado (1716–1755) (son of Ashipa/Esikpa)
- Ọba Gabaro (1755–1760)
- Ọba Akinsemoyin (c.1760-1775)
- Ọba Eletu Kekere (c1775 - 1780)
- Ọba Ologun Kutere (also Ologunkutere / Ologunkuture) (1780-1801) or until 1803
- Àlàfo ọdún láàrin Ologun Kutere àti Adele (c 1805 - c1810/11)
- Ọba Adele Ajosun (1811-1821)
- Ọba Oṣinlokun Ajan (Oshinlokun, Eshinlokun) (1821–1829)
- Ọba Idewu Ojulari (1829–1832) or until 1835
- Ọba Adele Ajosun (second term) (1835-1837)
- Ọba Oluwole (1837-1841)
- Ọba Akitoye (1841-1845)
- Ọba Kosoko (1845–1851)
- Ọba Akitoye (second term) (1851-1853)
- Ọba Dosunmu (1853–1885)
- Ọba Oyekan I (1885–1900)
- Ọba Eshugbayi Eleko (1901-1925)
- Ọba Ibikunle Akitoye (1925–1928)
- Ọba Sanusi Olusi (1928–1931)
- Ọba Eshugbayi Eleko (second term) (1931-1932)
- Ọba Falolu Dosunmu (1932–1949)
- Ọba Adeniji Adele (1949–1964)
- Ọba Adeyinka Oyekan II (1965–2003)
- Ọba Rilwan Akiolu (2003–present)
Itokasi
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ https://archive.org/details/slaverybirthafri00mann
- ↑ https://en.wikipedia.org/wiki/Oba_of_Lagos#cite_ref-JHK_2-0
- ↑ https://en.wikipedia.org/wiki/Oba_of_Lagos#cite_ref-Folami_3-0
- ↑ https://en.wikipedia.org/wiki/Oba_of_Lagos#cite_ref-Smith_4-0
- ↑ https://books.google.com/books?id=aqVbAAAAQAAJ&q=akitoye+benin+undisputed+right&pg=RA1-PA97
- ↑ https://archive.org/details/in.ernet.dli.2015.15075/page/n39/mode/2up?view=theater
- ↑ https://books.google.com/books?id=s1ceAQAAMAAJ&q=protectorate++%22Oba+of+Benin%22
- ↑ https://en.wikipedia.org/wiki/Oba_of_Lagos#cite_ref-8
- ↑ https://en.wikipedia.org/wiki/Oba_of_Lagos#cite_ref-9
- ↑ https://en.wikipedia.org/wiki/Oba_of_Lagos#cite_ref-10
- ↑ https://books.google.com/books?id=ric6OhxbCS0C&q=ashipa+oloriogun&pg=PA74
- ↑ https://en.wikipedia.org/wiki/Oba_of_Lagos#cite_ref-12