Jump to content

Kayode Olofinmoyin

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
(Àtúnjúwe láti Kayode Olukimo)
Kayode Olofin-Moyin
Administrator of Ogun State
In office
22 August 1996  August 1998
AsíwájúSam Ewang
Arọ́pòOlusegun Osoba

Kayode Olofinmoyin jẹ́ ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà àti Gómìnà Ìpínlẹ̀ Ògùn tẹ́lẹ̀.


    Ìgbésí ayé ìbẹ̀rẹ̀

    [àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

    A bí ọ̀gágun ojú omi Káyọ̀dé Ọlọ́fìn-móyìn ní Ilawe-Ekiti, ìpínlẹ̀ Ekiti, ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù karùn-ún, ọdún 1950.

    Lẹ́yìn ẹ̀kọ́ alakọ́bẹ̀rẹ̀ rẹ̀, ó forúkọ sílẹ̀ ní Annunciation Catholic School, Ikere-Ekiti ní ọdún 1965. Ó jáde ní ọdún 1969 pẹ̀lú ìwé ẹ̀rí ilé-ẹ̀kọ́ oníwè mẹ́wàá tí ó sì yege pẹ̀lú èsì ìdánwò tí ó moyan lori.

    Wọ́n gbà á sí ilé-ẹ̀kọ́ àwọn ọmọ ogun ti Naijiria ní ọdún 1971 gẹ́gẹ́ bí kàdéètì, ó sì parí ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní oṣù ọpẹ́ ní ọdún 1972, wọ́n sì yàn án sí ẹgbẹ́ ọmọ ogun ojú omi ti ilẹ̀ Nàìjíríà. Lẹ́yìn náà, ní sísẹ́ n tẹ̀lẹ́, ó gba àwọn ìdánilẹ́kọ̀ọ́ síwájú sí i. Kò pẹ́ tí ó fi ilé-ẹ̀kọ́ ọmọ ogun Nàìjíríà sílẹ̀ ní oṣù ọpẹ́ ní ọdún 1972, nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ ìdánilẹ́kọ̀ọ́ ní Midshipman NNS OBUMA (tí a mọ̀ sí NNS NIGERIA tẹ́lẹ̀). Ó parí ìdánilẹ́kọ̀ọ́ rẹ̀ ní oṣù Ọ̀wàrà ní ọdún 1973 [1]

    Ọ̀gágun kan tí a lè sọ pè ìwà ìmọ rẹ̀ kò ní òpin ní , ọ̀gágun ojú omi Olofin-Moyin tẹ̀síwájú Lẹ́yìn náà, ó lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ gíga ogun ní Abùjá, láàárín ọdún 1997 sí 1998.

    Olórí ọmọ ogun ojú omi Olofin-Moyin ń gòkè Si nínú iṣẹ́ tí ó yàn láàyò. Láti orí kàdéètì ní ọdún 1972, wọ́n gbé e ga sí Midshipman ní ọdún 1973; Sub-Lieutenant (1973 – 1977); Lieutenant (1977 – 1981); Lieutenant Commander (1981 – 1988); Commander (1988 – 1994) àti Captain Navy (1994)

    Díẹ̀ lára àwọn iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Aláṣẹ, NNS HADEJIA (Ọkọ̀ ojú omi Patrol), (1978 – 1979); Aláṣẹ, NNS RUWAN YARO (Ọkọ̀ ojú omi ìkẹ́kọ́ Cadets), (1984 – 1985); Aláṣẹ, NNS ENYIMIRI (A Corvette on ECOMOG Operation), Liberia, (1992 – 1993) àti Aláṣẹ, Ibùdókọ̀ ojú omi ojú omi, (1996 – 1997).

    Olórí ọmọ ogun Ojú Omi Olofin-Moyin tún ṣe àwọn iṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí Olórí Ọkọ̀ Ojú Omi (Iṣẹ́), Aláṣẹ Ọkọ̀ Ojú Omi Ìwọ̀ Oòrùn (1986 – 1988); Olórí Ibùdó, Kọ́lẹ́ẹ̀jì Ọkọ̀ Ojú Omi Nàìjíríà, Onura, Port Hacourt (1990 – 1992); Olórí Ọkọ̀ Ojú Omi, ECOMOG, Liberia (1994 – 1995) àti Olùdarí Iṣẹ́, Olú Ilé Iṣẹ́ Ọkọ̀ Ojú Omi, Èkó (1995 – 1996).

    Olùdarí Ìpínlẹ̀ Ògùn

    [àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

    Wọ́n yan adari Ọmọ-ogun ojú omi Kayode Olofin-Moyin gẹ́gẹ́ bí Olùdarí Ológun ti Ìpínlẹ̀ ògùn, Nàìjíríà láti oṣù kẹjọ ọdún 1998 sí oṣù karùn-ún ọdún 1999 nígbà ìjọba ológun ti Ọ̀gágun Abdulsalami Abubakar, ó sì fi agbára lé gomina tí wọ́n yàn Olusegun Osoba lọ́wọ́ ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba àwa ara wa Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà kẹrin . Ó kọ́ ilé ìjọba tuntun fún ìpínlẹ̀ Ogun, tí wọ́n ṣí ní ọjọ́ kẹtàdínlọ́gbọ̀n oṣù kẹrin ọdún 1999 kí wọ́n tó fi ìjọba lé gómìnà alágbádá lọ́wọ́.

    Ní oṣù bélú, ọdún 2002, ilé rẹ̀ ní erékùsù Victoria, ní ìlú Èkó jóná. [2]

    1. Empty citation (help)
    2. Yar'Adua's visit and Nigeria – UK relations (1) [Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]