Jump to content

Patrick Aga

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Patrick Aga ni wọ́n yàn gẹ́gẹ́ bí Aṣòfin fún agbègbè Nasarawa ti eka Ariwa (North) ti ìpínlẹ̀ Nasarawa, Nàìjíríà ní ìbẹ̀rẹ̀ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà Kẹrin, tí ó ń dije lati egbe Peoples Democratic Party (PDP). Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ní ọjọ́ kọkàndínlọgbọn oṣù karùn-ún ọdún 1999.[1]

Lẹ́yìn tí ó gba ìjókòó rẹ̀ ní Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin ní oṣù kẹfà ọdún 1999, wọ́n yàn án sí ìgbìmọ̀ lórí Ìwà, Ìdájọ́, Ọ̀rọ̀ Àwọn Obìnrin, Ìṣòwò, Ẹ̀kọ́, Àwọn Iṣẹ́ Àkànṣe àti Gbèsè Ìbílẹ̀ & Ajeji (igbákejì alága).


Ní àsìkò ìdìbò ọdún 2003, Aga gbé lọ sí ẹgbẹ́ Alliance for Democracy (AD) pẹ̀lú ìrètí láti di gómìnà Nasarawa lórí ìkànnì yẹn.

Lẹ́yìn ìdìbò naa, ẹgbẹ́ AD pín sí ẹgbẹ́ alátakò méjì.

Ní oṣù Kejìlá ọdún 2003 wọ́n yàn Aga gẹ́gẹ́ bí igbákejì alága orílẹ̀-èdè fún agbègbè Àríwá-Àárín nínú ẹgbẹ́ tí Olórí Adebisi Akande ń darí.[2]

  1. "Federal Republic of Nigeria Legislative Election of 20 February and 7 March 1999". Psephos. Retrieved 2010-06-24. [Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]
  2. Bolade Omonijo, Emmanuel Aziken & Olasunkanmi Akoni (17 December 2003). "Akande Emerges Lagos AD Faction Chairman, Akinfenwa Wins in Abuja.". Vanguard. Archived from the original on 2012-10-22. Retrieved 2010-06-25.  Unknown parameter |url-status= ignored (help)