Tunde Idiagbon
Tunde Idiagbon | |
|---|---|
| 6th Chief of Staff, Supreme Headquarters | |
| In office 31 December 1983 – 27 August 1985 | |
| Head of State | Muhammadu Buhari |
| Asíwájú | Alex Ekwueme as civilian Vice President of Nigeria |
| Arọ́pò | Ebitu Ukiwe |
| Governor of Borno State | |
| In office July 1978 – October 1979 | |
| Asíwájú | Mustapha Amin |
| Arọ́pò | Mohammed Goni |
| Àwọn àlàyé onítòhún | |
| Ọjọ́ìbí | 14 Oṣù Kẹ̀sán 1943 Ilorin, Northern Region, British Nigeria (now Ilorin, Kwara State, Nigeria) |
| Aláìsí | 24 March 1999 (ọmọ ọdún 55) Ilorin, Kwara, Nigeria |
| Ẹgbẹ́ olóṣèlú | None (military) |
| (Àwọn) olólùfẹ́ | Biodun Idiagbon |
| Alma mater | Nigerian Military School Pakistan Military Academy Nigerian Defence Academy Naval Postgraduate School |
| Military service | |
| Allegiance | Nigeria |
| Branch/service | Nigerian Army |
| Years of service | 1962–1985 |
| Rank | Major general |
| Battles/wars | Nigerian Civil War |
Babatunde "Tunde" Abdulbaki Idiagbon (abi ní ọjọ́ kẹrìnlá Oṣù Kẹsàn-án ọdún 1943 ó jáde làyè ní ọjọ́ kẹrìnlèlògùn Oṣù Kẹta Ọdún 1999) jẹ́ ọ̀gágun ní orílẹ̀ èdè Náìjíríà tí ó ṣiṣẹ́ bí Olùdarí ìṣàkóso kẹfà, ní olú Ilé-iṣẹ́ àwọn ọmọ ológun lábẹ́ ìṣàkóso ọ̀gágun Muhammadu Buhari tí o jẹ́ ààrẹ ológun fún orìlẹ̀ èdè Nàìjíríà láti ọdún 1983 sí ọdún 1985.
Ó tún jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ àgbà nínú ìjọba ológun ti Nàìjíríà láàrín ọdún 1966 àti 1979, tì a sì yàn-án gẹ́gẹ́bíi gómìnà ológun ti ìpínlẹ̀ Borno lábẹ́ ìjọba ológun Olusegun Obasanjo. [1]
Ìgbà Èwe rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Idiagbon tì bàbá rẹ̀ Hassan Dogo[1] ẹni tí ó ṣẹ̀wá láti ẹ̀yà Fúlàní àti ìyá rẹ̀ Áyìsátù Ìyábejì Hassan Idiagbon ni a bí ní ọjọ́ kẹrìnlá Oṣù Kẹsàn-án ọdún 1943 ní ìlú Ìlọrin, Ìpínlẹ̀ Kwara[2]. Ó lọ sí ilé ìwé alákọ̀bẹ̀rẹ̀ ti United Primary School, Ilorin láti ọdún 1950 sí ọdún 1952 àti Okesuna Senior Primary School , Ìlọrin, 1953-57. Ó lọ sí ilé ẹ̀kọ́ girama ti àwọn ológun Nàìjíríà láàrín ọdún 1958 sí ọdún 1962. [1]
Iṣẹ́ Rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Ológun
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ní ọdún 1962, Idiagbon darapọ̀ mọ́ Ẹgbẹ́ ọmọ ológun Nàìjíríà nípa lílọsí ilé ẹ̀kọ́ àwọn ọmọ ológun Nàìjíríà (NMTC). Ní oṣù kejí ọdún 1964, a yí orúkọ ilé ẹ̀kọ́ náà padà sí Nigerian Defence Academy (NDA).
Láti ọdún 1962 sí ọdún 1965, Ìdáàgbọn lọ kẹ́kọ̀ọ́ ní Ilé-ẹ̀kọ́ ọmọ ogun ti ìlú Pakistan, tí ó wà ní ìlú Kakul (PMA Kakul), Abbottabad, Pakistan, níbití ó ti kẹ́kọ̀ọ́ gboyè nínú ìmọ̀ ọrọ̀-ajé. Nígbà tó dé sí orílẹ̀ èdè Nàìjíríà láti Pakistan, wọ́n yàn án sípò alábòójútó kejì ní oṣù kẹrin ọdún 1965. Ó jẹ́ apàsẹ ìṣọ̀rí àwọn ọmọ ológun Kẹrin láti oṣù kẹjọ ọdún 1965 títí di oṣù kejì ọdún 1966. Ní ọdún 1966 ó kẹ́kọ̀ọ́ fún ẹ̀kọ́ ọmọ-ogun kékeré ní Ilé-ẹ̀kọ́ àwọn ọmọ ológun ti Nàìjíríà èyí tí ó wà ní ìlù Kàdúná. Láti ọdún 1966 si ọdún 1967 ó tún ṣiṣẹ́ ọ̀tẹlẹ̀múyẹ́ fún ìṣọ̀rí ọmọ ogun kẹrin, àti adarí gbogboogbò fún ìṣọ̀rí àwọn ọ̀tẹlẹ̀múyẹ́ kẹta, tí ó wá láti èyà àkọ́kọ́. Wọ́n gbé e ga sí ipò ọmọ ogun alàdè ní ọdún 1966. Ó kópa nínú Ogun Abẹ́lé ti ilẹ̀ Naijiria nìbití ó ti jẹ́ apàṣẹ káàfàtà fuń ẹgbẹ́ àwọn ọmọ ogun ti ìṣọ̀rí ogún láti Oṣù Kẹwàá ọdun 1967 sí oṣù kejì ọdún 1968. Lọ́dún 1968, wọ́n gbé e ga sí ipò ọ̀gágun. Ó jẹ́ olórí ẹgbẹ́ ọmọ ogunti ìṣọ̀rí ọgọ́fà lé márùn-ún láti ọdún 1968 sí ọdún 1970 - ẹ̀ka ẹgbẹ́ ọmọ ológun kan tó jẹ́ ẹ̀rùjẹ̀jẹ̀. [3]
Lọ́dún 1970, wọ́n gbé e ga sí ipò olórí. Ó di olórí ẹgbẹ́ àwọn ọmọ ogun àti igbákejì apáṣẹ káàfàtà fún ìṣí ẹgbẹ́ àwọn ọmọ ogun òǹkà kẹtàlélọ́gbọ̀n láti Oṣù Kẹta ọdún 1970 sí Oṣù Kẹta ọdún 1971 àti adarí ẹgbẹ́ àwọn ọmọ ogun ti ìṣí kọkàndínlọ́gbọ́n láti oṣù Kẹta ọdun 1971 sí Oṣù kejìlá ọdún 1972. Ní oṣù kínní ọdún 1973 ó ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀gá àwọn òṣìṣẹ́, ìkọ́ kínní àti lẹ́yìn náà, òṣìṣẹ̣ gẹ́gẹ́ bì ọ̀gá àgbà (PSO) ní ilé àwọn ọmọ ológun tí ó gajù lọ. Wọ́n gbe ga sí ipò alákòóso ní ọdún 1974. Ó di olùdarí àwọn ọmọ ogun ti ìṣí kẹtàlélọ́gbọ̀n àti ìkarùndínlógún lati oṣù kẹjọ ọdún 1975 si osù kẹjọ ọdún 1978. Ní ọdún 1976, Idiagbon lọ sí Ilé Ẹ̀kọ́ Ìṣàkóso àti Òṣìṣẹ́ ní Quetta, Pakistan, fún ìdánilẹ́kọ̀ọ́ síwájú sí i. Ní oṣù keje ọdún 1978, wọ́n gbé e ga sí ipò kọ́nẹ̀lì. A yàn-án sí ipò olùdarí ilé agbára àti bí a ti ń ṣètò ní olú Ilé-iṣẹ́ ìṣàkóso àwọn ọmọ ológun ní Oṣu Kẹwa ọdun 1979. [4]
Ní oṣù karùn-ún ọdún 1980, o gba ìgbéga sí ipò olórí àgbà fún ẹgbẹ́ àwọn ọmọ ológun. Ní ọdún 1981, ó lọ sí Ilé-ẹ̀kọ́ íjọba àpapọ̀ tí wọ́n ti ń kọ́ nìpa ètò ìmúlò àti ẹ̀kọ́ nípa ìgbésẹ̀ ní Kuru, Jos, ìpínlẹ̀ Plateau, Nàìjíríà àti ní ọdún 1982 o lọ si kẹ́kọ̀ọ́ nípa ìṣàkóso ètò àbò káríayé ní Ilé-ìwé gíga ti àwọn ọmọ ogun ojú omi ní ìlú Amẹ́ríkà. Ó jẹ́ akọ̀we fún àjọ àwọn ọmọ ológun ti orílẹ èdè Nàìjíríà láti ọdún 1981 sí ọdún 1983.
Gẹ́gẹ́ bí Olùṣàkóso ìpínlẹ̀ Borno
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Láti Oṣù Kẹjọ ọdún 1978 sí Oṣù Kẹwàá ọdún 1979, Olórí orílẹ̀ èdè ọ̀gágun Ọbásanjọ́ yan Ìdíàgbọn gẹ́gẹ́bí alákòóso (ipò tí à ń pè ní gómìnà báyìí) ti ìpínlẹ̀ Borno ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà. [4]
Olórí àwọn òṣìṣẹ́ fún Ilé àwọn Ọmọ Ogun tí ó gajù lọ.
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ọ̀gágun Muhammadu Buhari fi Ìdíàgbọn ṣe igbákejì rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi Olùdarí àwọn òṣìṣẹ́ ní ilé àwọn ọmọ ogun tó gajù lọ láti ọjọ́ kọkànlélọ́gbọ̀n Oṣu kejila ọdun 1983 sí ọjọ́ kẹtàdínlọ́gbọ̀n Oṣu Kẹjọ ọdun 1985. A ṣe àpèjúwe rẹ̀ gẹ́gẹ́bí ògbòǹtarìgì àti ògúnnágbòǹgbò ọmọ ológun tó ń dátọ́ lẹ́nu ìgbín , ó kó ipa ribiribi nìnú ìṣàkóso ti ọ̀gágun Buhari. Ìdiàgbọn gba ìgbéga sí ipò ọ̀gágun níọdun 1985[5].
Ó ṣàkóso gbogbo àwọn ohun tó ní ṣe pẹ̀lú ìjọba àpapọ, ọ̀rọ̀ òṣèlú, àti àwọn ẹ̀ka ìjọba lóríṣìrìṣǐ. [6] Idiagbon jẹ́ olùfilọ́lẹ̀, olùkéde àti fífìdímúlẹ̀ ọ́pọ́lọpọ̀ àwọn òfin ìjọba, lára wọn ni:
Gbígbógunti ìwà ìbàjẹ́ láwùjọ
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Àwọn ìpele márùn-ún ti gbígbógunti ìwà ìbàjẹ́ tí Idiagbon kéde tí ó sí gbé kalẹ̀ ni:
- Ìpele Kìíní - Ìdúró ní ìlà, tí a bẹ̀rẹ̀ ní ogúnjọ́ oṣù kẹta ọdún 1984
- Ìpele Kejì - Iṣẹ́ ṣíṣe, tí a bẹ̀rẹ̀ ní ọjọ́ kìńní oṣù karùn-ún ọdún 1984
- Ìpele kẹta -Jíjẹ́ olóòótọ́ àti ọmọ orílẹ èdè rere ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù kẹjọ ọdún 1984
- Ìpele Kẹrin - Gbígbógunti jẹgúdújẹrá àti lílo owó ìlú lọ́nà àìtọ́ ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù karùn-ún ọdún 1985
- Ìpele karùn-ún - Ìmọ́tótó àyíká, tí a bẹ̀rẹ̀ ní ọjọ́ kọkàndínlọ́gbọ̀n oṣù keje ọdún 1985
Ìyípadà owó àti ètò ìyípadà owó
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ní oṣù kẹrin ọdún 1984, Idiagbon kéde owó tuntun fún orílẹ èdè Nàìjíríà. Ó sọ pé owó tuntun náà á máa ní orúkọ kan náà, àmọ́ àwọ̀ owó náà á yàtọ̀ síra.
Ó tún kéde gbèdéke iye owó ilẹ̀ òkèrè tí àwọn ilé iṣẹ́ tàbí àwọn èèyàn lè pààrọ̀. Iye tí ẹnìkan lè pààrọ̀ ni ẹgbẹ̀rún méje [7,000] dọ́là. Ó sọ pé, ẹnikẹ́ni tó bá fẹ́ ṣẹ́ owó tó ju èyí lọ ní láti ṣàlàyé ibi tí owó náà ti wá, ó sì nílò àṣẹ láti ọ̀dọ̀ ìjọba.
Gẹ́gẹ́bí Ìdíàgbọn ṣe sọ, ohun tí ó ń fa akùdé bá ètò ọrọ̀ ajé orílẹ̀ èdè ní fífi ẹ̀yìn pọ̀n àti gbígbé owó orílẹ̀ èdè Nàìjíríà lọ sí ìlú mìíràn lọ́nà àìtọ́[7].
Òfin kíkó àwọn Ọjà wọlé làti Òkè Òkun
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ní ọdún 1984, Idiagbon lábẹ́ ìjọba ológun gbé òfin kalẹ̀ láti máa lo àwọn oun àlùmọ́nì ilẹ̀ Nàìjíríà láti fòpin sí kíkó wọlé làti òkè òkun. Wọ́n mú kí àti kó àwọn nǹkan wọlé láti òkè òkun lágbára gan-an. Ìdí èyí ni láti mú kí àwọn ilé iṣẹ́ tó wà lábẹ́lé náà ní ìdàgbàsókè tó gbọngbán.
Ètò Pípadà lọ sínú iṣẹ́ Àgbẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Bákańàn ni ọdún 1984, Idiagbon ni ó ṣaájú ètò ìjọba tí ó ní n ṣe pẹ̀lú kí àwọn èèyàn padà sí ìdí iṣẹ́ ọ̀gbìn ètò tí ìjọba gbé kalẹ̀ láti gba àwọn ará ìlú níyànjú láti padà sí tàbí tẹra mọ́ iṣẹ́ àgbẹ̀ èyí tí yó mú kí ońjẹ pọ̀ ní ọ̀pọ̀ yanturu tí yóò dẹ́kun ìṣẹ́ àti òṣì láwùjọ. [8]
Òfin ilẹ̀ òkèère
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Láti oṣù kínní ọdún 1984 sí oṣù kẹjọ ọdún 1985, Idiagbon ló ń ṣakoso gbogbo òfin tó ní n ṣe pẹ̀lú ilẹ̀ òkèrè pàápàá jùlọ lórí ọ̀rọ̀ ààbò. Ó ń darí títi àwọn ẹnu ibode tí ó wọ orìẹ̀ èdè Nàìjíríà, lílé àwọn tí wọ́n wọ orílẹ̀ èdè Naììjíríà lọ́nà àìtọ́ jáde, àti lílo àwọn ohun tó bà jẹ́ lẹ́yìn ìṣẹ̀lẹ̀ Umaru Dikko nílẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì.
Ó tún kópa nínú ìgbòkègbodò olóṣèlú. Ní orúkọ ìjọba ológun Nàìjíríà, ó fọwọ́ sí àdéhùn ìfọ̀sowọ́sowọ́pọ̀ lórí ètò ìfojúsùn àti ètò ìkọ́nilẹ́kọ̀ọ́ pẹ̀lú àwọn aṣojú làti ilẹ̀ Bulgaria ṣèbẹ̀wò lábẹ́ adarí ìlú náà Grisha Filipov ní ọdún 1984. Ó ṣaájú ìgbìmọ̀ kan ní ọdún 1984 sí Soviet Union láti pàdé olórí Soviet Konstantin Chernenko. [9]
Ìdìtẹ̀ gbàjọba tó wáyé ní ọdún 1985
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Lẹ̀hìn tí wọ́n ti lo oṣu ogún ní ipò, ìjọba ológun ti Bùhárí ni Ibrahim Babangida padà dojú ẹ̀ bolẹ̀ ní ọjọ́ kẹtàdínlọ́gbọ̀n Oṣu Kẹjọ, ọdun 1985. [10] A yọ Idiagbon kúrò nípò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bíi olùdarí àwọn ọmọ ológun tí ó wà ní ilé àwọn ọmọ ológun tí ó gajù, lẹ́yìn èyí wọ́n fi òfin ìsémọ́lé gbe fún ọdún mẹ́ta, lẹ́hìn ìdásílè rẹ̀ ó fẹ̀yìntì sí ìlú rẹ̀ Ilorin lẹ́yìn náà ó ń gbé ìgbé ayé gbòńkẹ́lẹ́. [11]
Ìgbésí ayé rẹ̀ Nígbàtí ó ti tójú bọ
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ní ọjọ́ kẹfà oṣù kẹta ọdún 1970, Idiagbon gbé Biodun Idiagbon (ọmọ Gamra) ní ìyàwó. Wọ́n ní àwọn ọmọkùnrin méjì àti àwọn ọmọbìnrin mẹ́ta papọ: Adekunle, Junior, Ronke, Mope ati Bola. [3] Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹta ọdún 1999, Idiagbon jáde láyé lọ́nà tó mú ìfunra tàbí awuyewuye dání.[12]
Àwọn Ẹ̀bùn àti àmì ẹ̀yẹ
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ajagunfẹ̀yìntì Idiagbon gba àwọn àmì ẹ̀yẹ àti ẹ̀bùn fún iṣẹ́ ribiribi tí ó ṣe. Àwọn àmì ẹ̀yẹ náà nìwọ̀nyí:
Àwọn ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- 1 2 3 https://www.premiumtimesng.com/news/top-news/322032-remembering-idiagbon-the-no-nonsense-military-general-who-ran-nigeria-with-buhari.html Àṣìṣe ìtọ́kasí: Invalid
<ref>tag; name "Premium Times Nigeria" defined multiple times with different content - ↑ http://allafrica.com/stories/199903290181.html
- 1 2 Uwechue, Ralph (1991). Africa Who's who. Africa Journal Limited. pp. 790.https://en.wikipedia.org/wiki/Tunde_Idiagbon#cite_ref-Uwechue_1991_790_3-1 Àṣìṣe ìtọ́kasí: Invalid
<ref>tag; name "Uwechue 1991 790" defined multiple times with different content - 1 2 Adeogun, Segun (1991). Who is Who in Kwara State. Ilorin, Nigeria:Segun Adeogun. pp. 110.https://en.wikipedia.org/wiki/Tunde_Idiagbon#cite_ref-Adeogun_1991_110_4-1 Àṣìṣe ìtọ́kasí: Invalid
<ref>tag; name "Adeogun 1991 110" defined multiple times with different content - ↑ http://www.mynewswatchtimesng.com/tunde-idiagbon-nigerias-unsung-hero/
- ↑ Inamete, Ufot (2001). Foreign Policy Decision-making in Nigeria. Susquehanna University Press. pp. 131.https://en.wikipedia.org/wiki/Tunde_Idiagbon#cite_ref-Inamete_2001_131_6-0
- ↑ http://www.upi.com/Archives/1984/04/24/Nigerians-bank-money-before-exchange-of-currency/2379451630800/
- ↑ Adediji, Banji (2013). Deeper insight into Nigeria's public administration. Author House. pp. 253.https://en.wikipedia.org/wiki/Tunde_Idiagbon#cite_ref-Adediji_2013_253_8-0
- ↑ Inamete, Ufot (2001). Foreign Policy Decision-making in Nigeria. Susquehanna University Press. pp. 134.https://en.wikipedia.org/wiki/Tunde_Idiagbon#cite_ref-Inamete_2001_134_9-0
- ↑ Olukoshi, Adebayo. [free Nigeria, Crisis Management under the Burhari Administration]. pp. 95–101. free.https://doi.org/10.1080%2F03056248508703655
- ↑ LeVan, A. Carl. Veto Players in Nigeria's Political History since Independence. pp. 55–119.https://www.cambridge.org/core/books/dictators-and-democracy-in-african-development/veto-players-in-nigerias-political-history-since-independence/65622D028C05694704A63A514C269081
- ↑ https://drbiggie.wordpress.com/2016/11/20/the-shocking-story-of-how-nigerias-de-facto-vice-president-idiagbon-died-at-56-why-buhari-burst-into-tears-during-his-burial-in-ilorin/
