Jump to content

Michael Adékúnlé Ajásin

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
(Àtúnjúwe láti Adekunle Ajasin)
Michael Adekunle Ajasin
Bust of Ajasin at Adekunle Ajasin University
Governor of Ondo State
In office
1 October 1979  31 December 1983
DeputyAkin Omoboriowo
AsíwájúSunday Tuoyo
Arọ́pòMichael Bamidele Otiko
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí(1908-11-28)28 Oṣù Kọkànlá 1908
Owo, Southern Nigeria Protectorate (now in Ondo State, Nigeria)
Aláìsí3 October 1997(1997-10-03) (ọmọ ọdún 88)
AráàlúNigeria
Ọmọorílẹ̀-èdèNigeria
Ẹgbẹ́ olóṣèlúUnity Party of Nigeria
OccupationPolitician

Michael Adékúnlé Ajásin ẹni tí a bí ní ọjọ́ kejìdínlọ́gbọ̀n Oṣù Kọkànlá ọdún 1908 tí ó sì jáde láyé ní ọjọ́ kẹta Oṣù Kẹ̀wàá ọdún 1997) jẹ́ olóṣèlú ọmọ orílẹ̀- èdè Nàìjíríà tó ti fìgbàkan ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí gómìnà Ìpínlẹ̀ Ondo láti ọdún 1979 sí 1983 lábẹ́ àsìá Ẹgbẹ́ Àjọṣepọ̀ ti Nàìjíríà (UPN) nígbà ìjọba ìbílẹ̀ Nàìjíríà Kejì .

Ìpilẹ̀sẹ̀ Ayé Rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bi Michael Adékúnlé Ajásin ni ìlú Ọ̀wọ̀, ni Ìpínlẹ̀ Òǹdó, gúúsù ìwọ̀-oòrùn Nàìjíríà ní ọjọ́ kejìdínlọ́gbọ̀n, oṣù kọkànlá, ọdún 1908. Ó lọ sí Ilé-Ẹ̀kọ́ girama ti St. Andrews, Ọ̀yọ́ láàrín ọdún 1924 sí ọdún 1927. Ó ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́bí olùkọ́ni fún ìgbà díẹ̀, lẹ́hìńnà a gbàá wọlé sí ilé ẹ̀kọ́ Fourah Bay College, tó wà ní Sierra Leone ní ọdún 1943, ó gba oyè ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ ti iṣẹ́ ọnà nínú èdè Gẹẹsi, Ìtàn òde òní àti ètò-ọrọ̀ ajé ní oṣù kẹfà, ọdún 1946. Lẹ́hìn èyí, ó lọ sí ibùdo tí a ti ń kọ́ nípa ìmọ̀ ẹ̀kọ́ ti Yunifasiti ti ìlú London níbití ó ti gba Ìwé-ẹ̀ri díplómà gíga nínú Ìmọ̀ Ẹ̀kọ́ ní oṣù kẹfà, ọdún 1947.

Ní ọjọ́ kejìlá oṣù kẹsàn-án ọdún 1947, wọ́n yan Ajasin gẹ́gẹ́ bí Olórí Ilé-ẹ̀kọ́ gíga Ìmade, tó wà ní ìlú Ọ̀wọ, níbi tí ó ti bẹ̀rẹ̀ ètò ìdàgbàsókè àti ìgbélárugẹ fún àwọn òṣìṣẹ́, títí kan fífi àwọn olùkọ́ ránṣẹ́ sí Yunifásítì kọ́lẹ́ẹ̀jì ti ìlú Ìbàdàn fún ìdánilẹ́kọ̀ọ́ síwájú sí i. Ní ọdún 1951, ó kọ ìwé kan tí ó di ìlànà ẹ̀kọ́ ti ẹgbẹ́ Action Group, tí ó ń gbèrò ẹ̀kọ́ ọ̀fẹ́ ní gbogbo ìpele. Ó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn olùdásílẹ̀ ẹgbẹ́ náà, àwọn ìlànà mìíràn tí o kópa nínú rẹ̀ ni gbígb òmìnira kúrò lọ́wọ́ àwọn òyìnbo amúnisìn, ètò ìlera káríayé, àti pípa ìṣẹ́ òun òṣì run nípasẹ̀ àwọn ìlànà ọrọ̀-ajé tí ó múná dóko. Ní oṣù Kejìlá ọdún 1962, ó fi ilé ẹ̀kọ́ Ìmádé sílẹ̀ láti di olùdásílẹ̀, olùsàkóso àti olórí àkọ́kọ́ ti Ilé-ẹ̀kọ́ Girama Ọ̀wọ̀ láti oṣù kíní ọdún 1963 sí oṣù kẹjọ ọdún 1975, nígbà tí ó fẹ̀yìntì.

Ó fẹ́ Babafunke Tenabe, olùkọ́ kan, ní ọjọ́ kejìlá oṣù kìíní ọdún 1939. Wọ́n bí ọmọ mẹ́rin, ọmọkùnrin méjì àti ọmọbìnrin méjì. Ọ̀kan lára àwọn Ọmọbìnrin rẹ̀, Arábìnrin Ọlájùmọ̀kẹ́ Anífowóṣe, di agbẹjọ́rò àgbà àti kọmíṣọ́nà fún ètò ìdájọ́ ní ìpínlẹ̀ Òǹdó.

Gẹ́gẹ́ bí olòṣèlú

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ajasin kópa nínú ìṣèlú Nàìjíríà kí Nàìjíríà tó gba òmìnira. Ní ọdún 1950, ó jẹ́ igbákejì ààrẹ orílẹ̀-èdè fún ẹgbẹ́ Action Group, a dìbò yàn-án gẹ́gẹ́ bí alàga kékeré fún agbègbè ki a tó padà yàn lẹ́yìn náà gẹ́gẹ́ bí alága ìjọba ìbilẹ̀ Ọ̀wọ̀ tí ó ní àwọn agbègbè bíi Ọ̀wọ̀, Idashen, Emùré Ilé, Ipele, Arimogija, Ute, Elerenla, Okeluse àti àwọn abúlé mìíràn. Wọ́n tún yàn án sí Ilé Aṣojùṣòfin Àpapọ̀ ní Èkó. Ó jẹ́ aṣòfin àpapọ̀ láti ọdún 1954 sí ọdún 1966 kí àwọn ológun tó gba ìjọba. Ní ọdún 1976, ó jẹ́ alága ìjọba ìbílẹ̀ Ọ̀wọ̀, ó sì dara pọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ Unity Party of Nigeria nígbà tí ìjọba ológun bẹ̀rẹ̀ ètò ìjọba tiwantiwa tuntun. Wọ́n yan Ajásin gẹ́gẹ́ bí gómìnà ní Ìpínlẹ̀ Ondo ní ọdún 1979, pẹ̀lú Akin Omoboriowo gẹ́gẹ́ bí igbákejì rẹ̀. Lẹ́yìn náà, èdè àìyedè bẹ́ sílẹ̀ láàárìn òun àti Omoboriowo, Omoboriowo sì bínú yalọ sínú Ẹgbẹ́ Àpapọ̀ Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà (NPN), níbi tí ó ti díje pẹ̀lú Ajásin ní ìdìbò ọdún 1983, wọ́n sì kọ́kọ́ kéde pé ó jẹ́ olùborí. Nígbà tó yá, wọ́n fagilé èsì ìdìbò náà, wọ́n sì búra fún Ajásin fún ìgbà kejì. Ajásin di ipò mú títí di ìgbà tí àwọn ológun gbajọba ní ọjọ́ kọkànlélọ́gbọ̀n oṣù Kejìlá ọdún 1983, èyí tí ó mú kí Ọ̀gágun Muhammadu Buhari ààrẹ.

Gẹ́gẹ́ bí gómìnà, Ajasin fọwọ́ sí òfin tí wọ́n fi dá Yunifásítì Ìpínlẹ̀ Ondo sílẹ̀ ní ọdún 1982 ní ìlú Ado-Ekiti, èyí tí ó wà ní Ìpínlẹ̀ Ekiti ti orílẹ̀ èdè Nàìjíríà lónìí.   Ní ọdún 2000, lákòkóò ìjọba Olóye Adébáyọ̀ Adéfaratì, a dá ilé-ẹ̀kọ́ gíga kan sílẹ̀ ní Àkùngbá Àkókó àti lẹ́hìńnà a sọ orúkọ rẹ̀ ní Yunifásitì Adekunle Ajasin láti bu ọlá fún-un. Ó tún ṣí Ilé Ẹ̀kọ́ gbogbonìṣe ti ìlu Ọ̀wọ̀ .

Ajásin jẹ́ olórí ẹgbẹ́ National Democratic Coalition tí a mọ̀ sí NADECO ní Nàìjíríà. Wọ́n dá ẹgbẹ́ náà sílẹ̀ láti fòpin sí ìjọba ológun Sani Abacha àti fún ìjọba láti bọ̀wọ̀ fún àṣẹ ìdìbò tí àwọn olùdìbò fún MKO Abiola . Ní ọdún 1995, ìjọba ológun Abacha gbe sí àtìmọ́lé pẹ̀lú àwọn ajìjàgbara mẹ́rìndínlógójì mìíràn fún ṣíṣe ìpàdé òṣèlú tí kò bófin mu. [1]

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. Empty citation (help)